Home / Àṣà Oòduà / Èèyàn ẹgbẹ̀rún kan àti irínwó dín mẹ́fà bá Kofi 19 rìn l’Amẹ́ríkà lópin ọ̀sẹ̀.

Èèyàn ẹgbẹ̀rún kan àti irínwó dín mẹ́fà bá Kofi 19 rìn l’Amẹ́ríkà lópin ọ̀sẹ̀.

Èèyàn ẹgbẹ̀rún kan àti irínwó dín mẹ́fà bá Kofi 19 rìn l’Amẹ́ríkà lópin ọ̀sẹ̀.

À fi kí á bẹ Ọlọ́run kó báwa dáwọ́ ibi dúró nílẹ̀ yìí àti lókèèrè to rí igbi gbogbo la lẹ́ni sí lórílẹ̀.
Gbogbo ìgbà ni àjàkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Kofi 19 ń pitú ọwọ́ rẹ̀ káàkiri àgbáyé o, bí ó se tun ti nawọ́jà rẹ̀ gbemi eeyan to pọ ni Amẹ́ríkà.

Ilẹ̀ Amẹ́ríkà tún ti ṣe àkọsílẹ̀ ikú ènìyàn ẹgbẹ̀rún kan àti irínwó dín mẹ́fà látàrí àrùn Kòrónáfairọ̀ọ̀sì

Èyí sì ti mú àpapọ̀ ènìyàn tó ti kú di ẹgbẹ̀rún méjì dín láàádọ̀rún lè ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ati mẹ́sàn an (88,709)

Àjọ tó ń mójú tó ìgbógun ti àjàkálẹ̀ àrùn ní Amẹ́ríkà (CDC) ló kéde èyí lọ́jọ́ Aìkú,

Wọ́n fi kún un pé mílíọ̀nù kan àti ẹgbẹ̀rún lọ́nà irínwó lé mẹ́tàdínláàdọ́rin àti márùn-únlélọ́gọ́ta ló ti ní àrùn ajániláyà pàtì méèmí ẹni lọ ọ̀hún. (1,467,065) èyí jẹ́ àfikún ẹgbẹ̀rún lọ́nà ogójì sí díẹ̀ sí èyí tí wọ́n ní tẹ́lẹ̀.

Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ló ní àkọsílẹ̀ àwọn tó kú jù nítorí àrùn Kofi 19 lágbàáyé.

Ṣáájú ni Ààrẹ ilẹ̀ Amẹ́ríkà tẹ́lẹ̀ rí Barack Obama ti ṣèkìlọ̀ lórí bí Ààrẹ Donald Trump se ń mú àrùn apinni léèmí náà Kòrónáfairọ̀ọ̀sì.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...