Home / Àṣà Oòduà / Adelabu tún gbé Ṣeyi Makinde lọ sí ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn

Adelabu tún gbé Ṣeyi Makinde lọ sí ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn

Adelabu tún gbé Ṣeyi Makinde lọ sí ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn

Fẹ́mi Akínṣọlá

Àwọn àgbà ní bí o bá nídíì,arúgbó ò gbọdọ̀ sunkún ọmú.
Bayo Adelabu ti ẹgbẹ́ òsèlú APC ní òun kò faramọ́ ìdájọ́ Àjọ Elétò Ìdìbò tó ní Ṣeyi Makinde ló wọlé nínú ìdibò tó kọjá.


Oloye Adebayo Adelabu ti ẹgbẹ́ oselu APC ti ni, òun kò faramọ idajọ ajọ eleto idibo to da igbẹjọ oun nù lórí idibo to gbe Ṣeyi Makinde wọle gẹ́gẹ́ bi gomina nipinlẹ Ọyọ. Lẹ́yìn ọjọ mọkanlelogun ti idajọ naa waye ni ilu Ibadan, ni Adelabu gbe ẹjọ lọ ile ẹjọ kotẹmilọrun.


Adelabu ati ẹgbẹ oselu APC sọ wi pe, magomago waye ninu idibo Ọjọ Kẹsan, Osu Kẹta, ọdun 2019, eleyii to gbe Ṣeyi Makinde wọle gẹgẹ bi gomina.
Adelabu wa n beere lọwọ ile ẹjọ kotẹmilọrun lati sọ wi pe oun lo ni ibo to pọju lọ ninu idibo sipo gomina ni ipinlẹ Ọyọ abi ki wọn tun ibo naa di.
Tí a ko ba gbagbe, Alaga igbẹjọ naa, Justice Muhammed Sirajo salaye pe awọn da ẹjọ ti APC pe mọ Ṣeyi Makinde nu nitori gbogbo àwọn ẹlẹri ti Adelabu pèé kò ní ẹri tó daju, amọ ti wọ́n ń sọ ahesọ lásán.

Iroyinowuro

About Lolade

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...