Home / Àṣà Oòduà / Àfikún owó oṣù nìkan lẹ̀rọ̀ ìyanṣẹ́lódì- NLC

Àfikún owó oṣù nìkan lẹ̀rọ̀ ìyanṣẹ́lódì- NLC

Àfikún owó oṣù nìkan lẹ̀rọ̀ ìyanṣẹ́lódì…NLC

Fẹ́mi Akínṣọlá

Ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ lorilẹede Nàìjíríà, NLC, ti sọ fún àwọn adari ẹgbẹ́ ọhun láwọn ipinlẹ pé kí wọ́n gbaradi fún ìyanṣẹ́lódì, bẹrẹ láti ọjọru, ọjọ Kẹrindinlogun oṣù Kẹwàá ọdún 2019.
Ẹgbẹ́ NLC ní òun yóò gunle iyaṣẹlodi náà tí ifọrọwerọ oun pẹlu Ìjọba àpapọ̀ kò bá so eso rere.


Nínú atẹjade kan tí ẹgbẹ́ náà fi sọwọ sí àwọn ẹka rẹ̀ ní àwọn ipinlẹ, ti akọwe àgbà ẹgbẹ́, Emmanuel Ugboaja fọwọ si, lóti sísọ lójú ọrọ náà.
Ẹgbẹ́ NLC ní, gẹ́gẹ́ bí ìwé tí òun ti kọ Ṣaájú sí àwọn ọmọ ẹgbẹ́ náà ní Nàìjíríà pe, ti ajọsọ egbẹ naa pẹlu ijọba apapọ lori afikun owo oṣu ko ba so eso rere, oun yoo bẹrẹ iyanṣẹlodi.

Ṣaájú ni ẹgbẹ awọn oṣiṣẹ ọhun ti beere afikun owo oṣu to jẹ ida mọkanla fun awọn oṣiṣẹ to wa ni ipele keje si mẹrinla, ati afikun owo oṣu ida mẹfa abọ fun awọn oṣiṣẹ ijọba to wa ni ipele karundilogun titi de ipele kẹtadinlogun.


Ni ọjọ kẹrinla oṣu karun un ọdun 2019 ni ijọba apapọ gbe igbimọ kan dide lati boju wo afikun ti ẹgbẹ oṣiṣẹ n beere fun.
Lẹ́yìn ọpọlọpọ ìpàdé àti ijiroro, ó jọ pé ẹ́gbẹ òṣìṣẹ́ àti Ìjọba àpapọ̀ kò tiì fẹnu ọrọ náà jona.

iroyinowuro

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...