Home / Àṣà Oòduà / Àwọn nọ́ọ̀sì fẹ̀hónú hàn l’America nítorí àìsí èròjà láti gbógun ti Covid-19

Àwọn nọ́ọ̀sì fẹ̀hónú hàn l’America nítorí àìsí èròjà láti gbógun ti Covid-19

Ẹgbẹ́ àwọn nọ́ọ̀sì kan, National Nurses United ti fẹ̀hónúhàn ní gbàgede Ilé Ìjọba America, White House, láti késí àwọn Gómìnà àti Ìjọba àpapọ̀ pé kí wọ́n ó pèsè èròjà ìdáàbòbò ara ẹni fún àwọn òṣìṣẹ́ ètò ìlera tó ń gbógun ti àrùn apinni léèmí coronaviurs.

Àwọn nọ́ọ̀sì náà sọ pe “ti ẹ ko ba daabo bo wa, a ko le daabo bo awọn alaisan wa’’.

Oríṣìríṣi àwòrán àwọn nọ́ọ̀sì àti dókítà tí Covid-19 ṣekúpa, àti àkọlé ni àwọn nọ́ọ̀sì náà gbé dání.

Ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́jọ nọ́ọ̀sì ló wà nínú ẹgbẹ́ náà, òun sì ni ẹgbẹ́ àwọn nọ́ọ̀sì tó tóbi jù l’Amẹ́ríkà

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...