Home / Àṣà Oòduà / Ladoja setan lati gba ipo gomina pada lowo Ajimobi ni kootu

Ladoja setan lati gba ipo gomina pada lowo Ajimobi ni kootu

Ladoja ati Ajimobi: Taani ipo gomina yoo ja mo lowo ni kootu?

Oniroyin: Olayemi Olatilewa
Orisun
Oniroyin: Twitter

Nibayii, won ti kede ojo ti won yoo pari ejo, eleyii ti o je asekagba, to wa laaarin Senato Rasheed Adewolu Ladoja ati Gomina ipinle Oyo, Senato Abiola Ajimobi eleyii to da lori eto idibo gomina to waye ninu osu kerin odun yii.

Ladoja lo gbe Gomina Abiola Ajimobi lo siwaju ile ejo kotemilorun tiribuna pelu esun wi pe magomago lo kun inu eto idibo to gbe Ajimobi wole gege bi gomina ipinle naa.

Leyin akojopo iwadii ati atotonu awon igun mejeeji ti oro naa kan, Aliyu Maiyaki to je adari igbimo tiribuna naa ti kede ojo ketadinlogbon osu kewaa odun yii (27/1015, ojo Tusde) gege bi ojo ti ejo naa yoo kase nile patapata.

Ninu eto idibo to waye losu kerin odun 2015, Gomina Ajimobi ti egbe oselu APC ni ajo INEC kede wi pe o bori pelu iye ibo 327 320. Nigba ti Ladoja ti egbe oselu Accord gbenu le e pelu iye ibo 254 520.
Eto idibo yii lo so Ajimobi di gomina akoko ti yoo wole fun igba keji si ipo gomina ni ipinle Oyo.

Ti e ko ba gbagbe, lojo kinni osu kokanla odun 2006. Ile ejo da Ladoja lare, o si paalase wi pe ki won da Ladoja pada si ipo re gege bi gomina leyin igba ti awon omo ile igbimo kan pawopo lati yo lona ti ko ye gege bi gomina ipinle Oyo nigba naa.

Eleyii fi han wi pe igba akoko ko ni yii ti Ladoja, eni odun mokanlelogorin (71), yoo ma gba ijoba pada nile ejo. Nje Ladoja yoo tun ri eleyii se loteyii?

Orisun
Oniroyin Twitter

About oodua

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

*

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...