Home / Àṣà Oòduà / Nítorí Àrùn Coronavirus Ìjọba Àpapọ̀ Ní Káwọn Arìnrìnàjò Láti Orílẹ̀èdè Amẹ́ríkà, Gẹ̀ẹ́sì, Faransé Àtorilẹ̀èdè Mọ́kànlá Míràn O Gbélé Wọn

Nítorí Àrùn Coronavirus Ìjọba Àpapọ̀ Ní Káwọn Arìnrìnàjò Láti Orílẹ̀èdè Amẹ́ríkà, Gẹ̀ẹ́sì, Faransé Àtorilẹ̀èdè Mọ́kànlá Míràn O Gbélé Wọn

Ṣé àwọn àgbà ní ogun tí yóó wọlé kóni, ọ̀nà là á ti í pàdé ẹ.
Gẹ́gẹ́ bíi ara ètò láti tètè rawọ́ ọwọ́jà àrùn apini ní mímí èémí Coronavirus wọlé, Ìjọba orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti gbẹ́sẹ̀lé ìrìnàjò láti àwọn orílẹ̀-èdè Mẹ́tàlá kan wọ orílẹ̀-èdè Naijiria.

Ohun tí èyí túmọ̀ sí ni pé kò sí àwọn arìnrìnàjò láti àwọn orílẹ̀-èdè mẹ́tàlá náà tó gbọdọ̀ wọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Àwọn orílẹ̀-èdè tí ọ̀rọ̀ kàn ni orílẹ̀-èdè China, Italy, Iran, South Korea, Spain, Japan, Faranse, Germany, Amẹrika, Norway, ilẹ Gẹẹsi, Netherlands ati orilẹede Switzerland.

Ìjọba àpapọ̀ ní àwọn gbé ìgbésẹ̀ yìí lórí àwọn orílẹ̀-èdè tó jẹ wí pé iye àwọn èèyàn tó ti fara kó àrùn Coronavirus ti ju ẹgbẹ̀rún kan lọ.

China 82007
Italy 27980
Iran 16169
South Korea, 8320
Spain 11178
Japan 829
Faranse 6573
Germany 6012
Amẹrika 3536
Norway 1169
ilẹ Gẹẹsi 1954
Netherlands 1705
Switzerland 2650
Alága ìgbìmọ̀ amúṣẹ́yá tí Ìjọba àpapọ̀ gbé kalẹ̀ lórí pípalẹ̀mọ́ àrùn Coronavirus kúrò lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà (Presidential Task Force on COVlD-19) ṣàlàyé fáwọn oníròyìn nílùúu Abuja pé àyẹ̀wò tó múnádóko yóó máa wáyé fún gbogbo àwọn èèyàn tó bá wọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lẹ́yìn àbẹ̀wò sáwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí; tí wọn yóó sì fi wọ́n sínú àhámọ́ ìyàsọ́tọ̀ àti àyẹ̀wò fún ọjọ́ mẹ́rìnlà.

Bákan náà ni Ìjọba àpapọ̀ tún ṣàlàyé pé àṣẹ yìí ló bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ẹsẹ̀ múlẹ̀, bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ Sátidé, ọjọ́ kọkànlélọ́gún oṣù kẹta ọdún 2020.

Bákan náà ni wọ́n tún fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, lásìkò tí àṣẹ yìí yóó fi fìdí múlẹ̀, kò ní sí ààyè à ń fún ẹnikẹ́ni ní ìwé àṣẹ ìwọ̀lú-gbélùú tí a mọ̀ sí físà.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...