Home / Àṣà Oòduà / Orí kó ènìyàn márùn-ún yọ lọ́wọ́ coronavirus l’Ekoo

Orí kó ènìyàn márùn-ún yọ lọ́wọ́ coronavirus l’Ekoo

Orí kó ènìyàn márùn-ún yọ lọ́wọ́ coronavirus l’Ekoo
Ìròyìn láti ọwọ́ Yínká Àlàbí

Alaisan marun-un ninu awon ti arun buruku covid-19 ti n ba finra lati bii ose meloo kan seyin gba idande. Yoruba bo “won ni alaare ko ki n ra si inu yara, bi o segun aisan, yoo fi ese ara re rin jade, bi o ba si yiwo naa, won a gbe oku re jade”.

Eyi lo sele si awon marun-un ti arun coronavirus ti n ba poo, ti won si segun arun naa, nitori pe gbogbo ayewo ti won se fun won lera-lera si gbee pe aisan naa ko si lara won mo.

Minisita eto ilera Dokita Osagie Ehanire ati ajo NCDC se tun n parowo si gbogbo omo Naijiria, won ni arun naa ko tii ni oogun kan gbogi nipa idi eyi, ki awon eniyan so ewe agbeje mowo. Ki onikaluku si gbe inu ile re gege bi gbogbo eka ijoba se n forere.

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...