Home / Àṣà Oòduà / O̩wó̩ pálábá 185 nínú o̩mo̩ e̩gbé̩ òkùnkùn ségí l’Eko

O̩wó̩ pálábá 185 nínú o̩mo̩ e̩gbé̩ òkùnkùn ségí l’Eko

O̩wó̩ pálábá 185 nínú o̩mo̩ e̩gbé̩ òkùnkùn ségí l’Eko
Yínká Àlàbí

Komisona olopaa ni ipinle Eko, Ogbeni Hakeem Odumosu tenu moo ipinle Eko ko ni faaye gba egbe okunkun rara.


Eyi lo faa to fi tete pakiti mole lati gbogun ti awon omo naa bi olobo se taa.
Lati ipari osu karun-un ni iroyin ti n kan ago olopaa pe awon egbe okunkun Eiye ati Aiye n gbena woju ara won.


Awon egbe yii si n fi ibon ati awon nnkan oloro miiran pa ara won paapaa ni agbegbe Ikorodu.


Ija miiran tun fe bere ni olobo ta awon olopaa ni eyi to si mu ki “owo palaba awon omo egbe marundinlaadowaa (185) segi”.
Agbegbe Shagamu,Igbogbo,Ibeshe, Ipakodo,Agbowa ati bee bee lo ni owo ti te awon omo yii ni ilu Ikorodu.

Awon egbe ti owo awon olopaa ti te awon omo won ju ni Eiye, Aiye, Kk, Buccaneers ati Vikings confraternity.


Die ninu awon Oloye egbe towo olopaa te ni Gbadamosi Mohammed, Onibudo Afeez,Habeeb Isa,Felix Igwoke, Taiwo Iyanu ati Adeoye Daya.
Awon olopaa gba ibon pisitu oyinbo mejo,ibon ibile kan pelu awon ohun ija oloro lorisiirisii.
Awon olopaa ni awon ti owo te naa ko ni pe foju ba ile-ejo.

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...