Home / Àṣà Oòduà / Seyi Makinde ṣe àbẹ̀wò sí ibùdó ìtọ́jú èèyàn 200 tí ọlọ́pàá tú sílẹ̀ ní ilé Ọlọ́rẹ

Seyi Makinde ṣe àbẹ̀wò sí ibùdó ìtọ́jú èèyàn 200 tí ọlọ́pàá tú sílẹ̀ ní ilé Ọlọ́rẹ

Seyi Makinde ṣe àbẹ̀wò sí ibùdó ìtọ́jú èèyàn 200 tí ọlọ́pàá tú sílẹ̀ ní ilé Ọlọ́rẹ

Fẹ́mi Akínṣọlá

Gómìnà ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́
Seyi Makinde ti se àbẹ̀wò sí ilé Ọlọrẹ tó wà ní àdúgbò Ọ̀jọ́ nílùú Ibadan .
Bẹ́ẹ̀ bá gbàgbé, ilé yìí ni ọwọ́ àwọn ọlọ́pàá ti tẹ èèyàn mẹ́rin tí wọ́n kó àwọn èèyàn ní ìgbèkùn lọ́jọ́ Ajé.


Èèyàn okòólénígba àti marùn ún ni wọn tú sílẹ̀ nínú ilé náà, tí wọ́n tún ń lò bíi mọ́sálásí.
Lásìkò tó se àbẹ̀wò síbi ìṣẹ̀lẹ̀ náà ni Gómìnà Makinde ti pàṣẹ pé kí wọ́n wó Mọsalasi ọ̀hún pátápáta.
Bákan náà ló tún ṣe àbẹ̀wò sí ibùdo tí wọ́n tí ń se ìtọ́jú àwọn èèyàn ti wọn tu silẹ ninu igbekun ni mọsalasi ọhun.

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...