Home / Àṣà Oòduà / Arábìnrin omo odún méèdógbòn, tí ó tún jé a fi ewà s’oge, Chidimma Leilani Aaron ti gba àmì èye gégé bíi omidan àkókó ní orílè èdè Nìjíríà tí odún 2018.

Arábìnrin omo odún méèdógbòn, tí ó tún jé a fi ewà s’oge, Chidimma Leilani Aaron ti gba àmì èye gégé bíi omidan àkókó ní orílè èdè Nìjíríà tí odún 2018.

,Chidimma Leilani Aaron, omo odún méèdógbòn láti ìpínlè Enugu ti tayo àwon métàdínlógún (17) tí won jo díje fún omidan àkókó ní orílè èdè Nìjíríà ti odún yí. O di eni kejìlélógójì tí yóò gba àmì èye yí ó sì lo ilé pèlú mílìònù méta náírà.
Ameh Rose ni ó se ipò keta tí Dunu sì se ipò kejì.
Gégé bí iwé ìròyìn daily times se se agbáterù rè, àjòdún tí ó máa n wáyé ní odoodún yí wáyé ní ilé ìtura ní ìlú Eko tí a mò sí Eko hotel. Òpòlopò àwon gbajúgbajà ènìyàn ni ô sì lo fún ojú lóúnje níbè.
Àwon Adájó ibè náà ni Rita Dominic, Ruchard Mofe Damijo, Olisa Adibua, Leesi Peter Vigbooro, Konye Nwabogor, Fade Ogbunro àti béè béè lo.
Ebuka àti Kayla Oniwo ni ó sì se agbáterù rè.

About Awo

x

Check Also

Aáyẹ tí ó de bá àṣà

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àṣà máa ń yí padà nípa aṣo wíwọ̀, ìgbéyàwó, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ, lóde-òní, ètò ẹ̀kọ́ àti ìwà ọ̀làjú tó gbòde kan ti ṣe àkóbá fún àṣà ní àwọn ọ̀nà wọ̀nyí: (a) Ìwọsọ wa kò bójú mu mọ́. (b) Àṣà ìkíni wa kò ní ọ̀wọ̀ nínú mọ́. (d) Kí’yàwó ilé má mọ oúnjẹ ìbílẹ̀ ṣè mọ́. (e) A kò mọ ìtumọ̀ àrokò tí a ń kọ́ àwọn ọmọ wa mọ́. (ẹ) A kò fi èdè ...