Ní òwúró ojó àíkú tí se èní,ojó kokàndínlógbòn osù keje odún 2018 ni òjò yí bèrè tí ó sì kò tí kò dáké di bíi agogo márùn-ún ìròlé.
Èyí fa kí àgbàrá ya wo ilé tí ó pò ní òpópónà Ede sí ifè, àti ònà tí a mò sí road 7, àti àwon ònà míràn, Ó tilè ti férè gba ilé míràn lówó onílé.
Tí ó bá je wípé ó ńkó wólo ni Ó sì dára, sùgbón kò wó lo bíkòse wípé ó dúró sí ojú kan tí kò sì lo, báwo ni àwon tí ó wà nínú ilé se ma jáde àti wípé báwo ni àwon tí ó wà ní ìta se ma w’olé?
Ìsèlè yí, nínú ìwádìí a gbó wípé èyí kó ni àkókò tí omi ma w’olé tí àgbàrá sì ma wo sóòbù ní ilé ifè ìlú tí ó wà ní ìpínlè Òsun ní orílè èdè Nìjíríà.
Kí ni ó le fa èyí? Sé ònà tí kò dára ni àbí àílè se ònà tí ó ye kí àgbàrá ma gba, èyí mà le poo, ní ìlú tí mùndùnmúdùn gbé ń sàn fún wàrà àti oyin, “èbè ni a be àwon ìjoba wa kí won bá wa mójú tó àwon ònà yí nítorí olórun” báyìí ni àwon ará ìlú ńké.
Àṣà Oòduà Àṣà Oòduà

Ko tiri, me man koru ye n’fe