Home / Àṣà Oòduà / Buhari bá ìpínlè̩ Eko ké̩dùn

Buhari bá ìpínlè̩ Eko ké̩dùn

Buhari bá ìpínlè̩ Eko ké̩dùn – Ìròyìn lati o̩wó̩ Yínká Àlàbí

Ojo buruku esu gbomi mu ni ojo isinmi oni je fun awon ara agbegbe Amuwo Odofin ni adugbo FESTAC.
Ijamba ina naa bere ni aago mesan-an aaro. Opa epo ni won lo dede bu gbamu ti ina so.


Ina naa ti mu emi ti ko din ni mejidinlogun lo.
Opo dukia ti ko niye lo ti ba isele buruku naa lo.
Aare Mohammadu Buhari naa ranse ibanikedun si ijoba ipinle Eko. O si ba gbogbo ebi to padanu eniyan won kedun.


Komisona olopaa ni ipinle Eko, Ogbeni Akeem Odumosu ni ijamba ina naa sele latiari moto akoyepe nla kan to fagidi koja ni adugbo naa. O ni kii se awon to n doju ija ko ilu bii boko haram lo dana si opa epo naa gege bi awon kan se n gbee pori enu lori ero ayelujara.
Ki Eledua ma se je ki a ri iru re mo.

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...