Ìrọ̀rùn dé, Yínká Ayéfẹ́lẹ́ le è dúró kọrin báyìí
Ẹ̀dá tí tó bá sì wà lókè èèpẹ̀ tó ń ṣẹ̀mí, ìrètí kò pin fúnrúfẹ́ onítọ̀ùn, bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́ lọ̀rọ̀ rí fún gbajúgbajà olórin jùjú n-nì, Yínká Ayéfẹ́lẹ́ bí ó ti jẹ́ pé ó ti le è nàró báyìí lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ tó bá wù ú.
Èyí kò ṣẹ̀yìn kẹ̀ẹ̀kẹ́ ìgbàlódé kan tó ní àwọn èròjà ìrọ̀rùn tó ṣe é yí sí ọ̀tún àti òsì, òkè àti ilẹ̀, ibi tó bá sì wu èèyàn, ló le è yí kẹ̀ẹ̀kẹ́ náà sí.
Yínká Ayéfẹ́lẹ́ , ló kéde pé ó ti rọrùn fún òun báyìí láti rìn pẹ̀lú kẹ̀ẹ̀kẹ́ tuntun náà lójú òpó Sítágíràmù rẹ̀ lọ́jọ́ Ẹtì.
Ó fikún un pé ẹlẹ́yinjú àánú kan, tó pé orúkọ rẹ̀ ní Hon Obama Oludare Akande ló fún òun ní kẹ̀ẹ̀kẹ́ tuntun náà láti orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà.
Ayéfẹ́lẹ́ ní “Mo lè dúró kọrin níbikíbi báyìí pẹ̀lú kẹ̀ẹ̀kẹ́ tuntun náà, ‘action’ bẹ̀rẹ̀ báyìí, mo dúpẹ́ púpọ̀ lọ́wọ́ Dáre Obama.”
![](https://asa.ooduarere.com/wp-content/uploads/2020/08/yinka.jpg)
Akọrin Tùǹgbá náà fikún un pé “ìrọ̀rùn dé bá mi gidi báyìí pẹ̀lú kẹ̀ẹ̀kẹ́ tuntun náà, Dáre Obama tún ti fún mi ní ìrètí láti rìn padà,.”
Ó wá gbàdúrà fún Aláànú náà pé kò ní mọ ìnira nílé ayé rẹ̀.
Bẹ́ẹ̀ bá gbàgbé, ó ti lé ni ogún ọdún tí gbájúmọ́ akọrin ẹ̀mí náà ti pàdánù ọ̀pá ẹ̀yìn rẹ̀, tí kò sì leè rìn mọ́ nítorí ìjàmbá ọkọ̀ tó wáyé.
Fẹ́mi Akínṣọlá