Home / Àṣà Oòduà / Ọdún orò gbìnà yá, ìdájí ní àwọn olórò yóò fi máa yíde ìlú níṣẹ̀yin

Ọdún orò gbìnà yá, ìdájí ní àwọn olórò yóò fi máa yíde ìlú níṣẹ̀yin

Fẹ́mi Akínṣọlá

Ṣe aifẹsọ kebosi,lai rẹni jo o,ati pe n ta o ba fẹ o bajẹ,o ni bi o ṣe yẹ ka ṣe e,eyi lo bi atunse abẹnu lati fopin sawuye wuye to waye latari aawọ to suyọ laarin awọn onisese ati awọn ẹlẹsin meji ti o ku(Kitẹẹni ati Musulumi).
Wayi o, igbakeji alaga fun ẹgbẹ agbaagba nilu Isẹyin, Alhaji Bọlaji Kareem, ti kede pe ija ti dopin, ogun si ti tan lori aawọ ọrọ sise nilu Isẹyin.
Kareem, ẹni to soju Asẹyin nibi ipade ipẹtu saawọ kan ti ẹgbẹ agbaagba naa seto salaye pe, lasiko to n ba lroyin Owurọ Yoruba sọrọ ni, awọn igbimọ Imaamu ati Alfa nilu Isẹyin, to fi mọ ẹgbẹ ẹlẹsin ọmọlẹyin Kitẹẹni,CAN atawọn
abọrẹ oro mẹrẹẹrin nilu naa, lo peju sibi ipade ọhun.

Nibi ipade naa lo ni wọn ti fẹnu ko lati jẹ ki ogun o sinmi, ti awọn oloro yoo si maa se oro wọn lati aago marun aabọ irọlẹ si marun idaji, ti wọn ko si ni yaju si ẹnikẹni.
Bakan naa, etutu oro ti gbera nilu Isẹyin lọjọ Aje pẹlu bibẹ aja sidi Ogun to wa loju ọja ilu naa.

http://iroyinowuro.com.ng/2019/09/19/odun-oro-gbina-ya-idaji-ni-awon-oloro-yoo-fi-maa-yide-ilu-ni%e1%b9%a3eyin/

About ayangalu

x

Check Also

Aáyẹ tí ó de bá àṣà

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àṣà máa ń yí padà nípa aṣo wíwọ̀, ìgbéyàwó, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ, lóde-òní, ètò ẹ̀kọ́ àti ìwà ọ̀làjú tó gbòde kan ti ṣe àkóbá fún àṣà ní àwọn ọ̀nà wọ̀nyí: (a) Ìwọsọ wa kò bójú mu mọ́. (b) Àṣà ìkíni wa kò ní ọ̀wọ̀ nínú mọ́. (d) Kí’yàwó ilé má mọ oúnjẹ ìbílẹ̀ ṣè mọ́. (e) A kò mọ ìtumọ̀ àrokò tí a ń kọ́ àwọn ọmọ wa mọ́. (ẹ) A kò fi èdè ...