Home / Àṣà Oòduà / Àdúrà làsìkò yí gbà pẹ̀lú ìfaradà láti ṣẹ́gun àrùn apinni léèmí Coronavirus–Ààrẹ Buhari

Àdúrà làsìkò yí gbà pẹ̀lú ìfaradà láti ṣẹ́gun àrùn apinni léèmí Coronavirus–Ààrẹ Buhari

Ààrẹ Buhari kí àwọn ọmọ Nàìjíríà kú àfaradà bí gbogbo nǹkan ṣe ń lọ lásìkò Coronavirus yìí

Nínú ọ̀rọ̀ ìkínni kú ọdún Àjíǹde tó fi ṣọwọ́ sáwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà

Ààrẹ Buhari ṣàlàyé pé ìgbáyégbádùn àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kìí ṣé oun tó ṣe é dúnàádúrà lé lórí ṣùgbọ́n ìgbésẹ̀ ààbò àti àlàáfíà aráàlú ṣe kókó.
Ààrẹ fi kún un pé, ó wu òun kí wọ́n jáde ṣọdún Àjíǹde, ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Covid 19 yìí ń gbẹ́mìí kúkúrú gígùn, o sì jẹ́ ohun ìbànújẹ́.
Ààrẹ wá fikún un pé,ki àwọn ènìyàn o tẹ̀lé òfin kónílé-ó-gbélé tí Ìjọba ti pàṣẹ kónílé-ó-gbélé o.

Àdúrà làsìkò yí gbà pẹ̀lú ìfaradà láti ṣẹ́gun àrùn apinni léèmí Coronavirus–Ààrẹ Buhari

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

ÌKéde ní Yàjóyàjó láti Ilẹ̀ ÌJẹ̀ṣà

Ìkéde ní Yàjóyàjó láti Ilẹ̀ Ìjẹ̀ṣà

Ní ìtẹ̀síwájú orò ìwúyè Ọwá Obòkun Àdìmúlà ilẹ̀ Ìjẹ̀ṣà, Ọwá Clement Adésuyì Haastrup, wọ́n ti kéde ìṣéde jákèjádò ìlú Iléṣà. Gẹ́gẹ́ bí Olóyè Àgbà Ọlálékan Fọ́lọ́runṣọ́ tí wọ́n jẹ́ Loro ilẹ̀ Ìjẹ̀ṣà ṣe kéde, ìṣéde náà yóò bẹ̀rẹ̀ ní aago mẹ́jọ alẹ́ òní Ọjọ́ Ẹtì, Ọjọ́ kọkànlá títí di aago mẹ́fà Òwúrọ̀ ọjọ́ Àbámẹ́ta, ọjọ́ Kejìlá oṣù kẹrin (8pm of April 11 to 6am of April 12, 2025) Kí eku ilé ó gbọ́, kó sọ fún toko o!!! Gbogbo ènìyàn ...