Home / Àṣà Oòduà / Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn wọ́gilé ìyọnípò Oshiomole gẹ́gẹ́ bíi alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC

Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn wọ́gilé ìyọnípò Oshiomole gẹ́gẹ́ bíi alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC

Ọ̀rọ̀ fini lògbòlògbò yini nù lọ̀rọ̀ ọ Alága gbogbo gbòò ẹgbẹ́ òsèlú APC dà báyìí o, bí Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn ìlú Abuja ti ní Adams Oshiomhole sì ni Alága gbogbo gbòò fún ẹgbẹ́ òṣèlú APC.

Ìgbìmọ̀ ẹlẹ́ni mẹ́ta tó ń gbọ́ ẹjọ́ náà, tí adájọ́ Abubaka Datti Yahaya kó sòdí wọ́gilé ẹjọ́ tí ilé ẹjọ́ gíga ìlú Abuja dá Ṣaájú, léyìí tó yọ Oshiomole nípò gẹ́gẹ́ bí Alága ẹgbẹ́ ọ̀hún.

Ṣaájú ni oshiomole ti rọ ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn náà láti gbé ìdájọ́ ìyọnípò rẹ̀ náà tì ṣí ẹ̀gbẹ́ kan.

Nígbà tó ń gbé ìdájọ́ rẹ̀ kalẹ̀, adájọ́ náà kìlọ̀ fún àwọn tí ọ̀rọ̀ ọ̀hún kàn láti má gbé ìgbésẹ̀ tí yóó tako ìdájọ́ tó gbé kalẹ̀.

Lẹ́yìn náà ló rọ àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú láti máa yanjú aáwọ̀ tó bá wà láàrin wọn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìyá dípò kí wọ́n máa yọ ilé ẹjọ́ lẹ́nu.

http://iroyinowuro.com.ng/2020/03/17/ile-ejo-kotemilorun-wogile-iyonipo-oshiomole-gege-bii-alaga-egbe-o%e1%b9%a3elu-apc/

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

seun kuti

Orí kó Seun Kuti yọ kúrò lọ́wọ́ ikú ní yàrá ìgbàlejò US

Mary Fágbohùn Olórin Afrobeat Seun Kuti ti fi ìrírí ibanuje ọkàn rẹ̀ ní orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà han nígbà tí ọta ibọn kan gúnlẹ̀ lójú fèrèsé yàrá igbalejo rẹ̀. O salaye ibapade to ba ni lẹru naa lori oju-iwe Instagram rẹ, o fi fidio ferese ti ọta ibọn naa bajẹ ati iho re han. Seun, ẹni ti o ṣalaye iyalẹnu, beere iwoye ti aabo ni Amẹrika. Ninu fonran naa, Seun Kuti sọ pe oun wa ninu yara igbalejo, ti oun n sinmi, ...