Home / Àṣà Oòduà / Ìròyìn Òrofó ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

Ìròyìn Òrofó ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

1 Ààrẹ Buhari yóò dé lónìí láti orílẹ̀ èdè China.

2 Ọ̀jọ̀gbọ́n Ọ̀ṣínbàjò gba àlejò àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tí wọn gbé igbá orókè nínú ìdíje ìmọ̀ ẹ̀rọ ìgbàlódé.

3 Àwọn oníròyìn ń fi ìròyìn burúkú bá ìjọba Buhari jẹ́ – Alákòóso

4 Àwọn olùdíje ipò àarẹ nínú ẹgbẹ́ PDP yóò yọnu si ẹni ti o ba gbégbá orókè.

5 Mo ní ọgbọ́n ìṣèlú ju Buhari lọ – Turaki

6 Ìdìbò Ọ̀ṣun : Falae sọ ìdí tí àwọn olùdìbò ṣe gbọ́dọ̀ dìbò fún ẹgbẹ́ SDP yàtọ̀ di ẹgbẹ́ APC.

7 Oshiomole bẹnu àtẹ́ lu bí àwọn ọlọ́páà ṣe lọ tú ilé alàgbà Clark.

8 Ilé iṣẹ́ ọlọ́páà yọ àwọn ọlọ́páà tí wọn tú ilé alàgbà Edwin Clark.

9 Ilé iṣẹ́ ọlọ́páà gbé àwọn ẹni afurasí méjì-dín-lógún tí wọn dáná sun ilé iṣẹ́ ọlọ́páà ni ìlú Iwo lọ sí ilé ẹjọ́.

10 Ẹgbẹ́ APC ni Ìpínlẹ̀ Imo yóò lo ètò Ìdìbò gbangba-làṣá-ń-ta láti yan olùdíje gómìnà.

11 Àwọn olùdìbò mílíọ̀nù ó lè ní kò ì tíì wá gba káàdì Ìdìbò alálòpẹ́ ni Ìpínlẹ̀ Èkó – INEC.

12 Ẹgbẹ́ Ọdọ APC rọ àwọn ìgbìmọ́ kí wọn dín owó ìdíje kù.

13 Èrò bílíọ̀nù mẹ́rin ó lé ní bàálù gbé ní ọdún 2017 – IATA

14 Orílẹ̀ èdè India fọwọ́ sì kí ọkùnrin fẹ́ ọkùnrin gẹ́gẹ́ bí aya.

15 Orílẹ̀ èdè China yóò dá okoòwò tí ó lé ní tírílíọ̀nù méjì Náírà sí ilẹ̀ adúláwọ̀.

Ayé wa kò ní dàrú lágbára ELÉDÙMARÈ.. Àmín.

About Awo

x

Check Also

Aáyẹ tí ó de bá àṣà

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àṣà máa ń yí padà nípa aṣo wíwọ̀, ìgbéyàwó, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ, lóde-òní, ètò ẹ̀kọ́ àti ìwà ọ̀làjú tó gbòde kan ti ṣe àkóbá fún àṣà ní àwọn ọ̀nà wọ̀nyí: (a) Ìwọsọ wa kò bójú mu mọ́. (b) Àṣà ìkíni wa kò ní ọ̀wọ̀ nínú mọ́. (d) Kí’yàwó ilé má mọ oúnjẹ ìbílẹ̀ ṣè mọ́. (e) A kò mọ ìtumọ̀ àrokò tí a ń kọ́ àwọn ọmọ wa mọ́. (ẹ) A kò fi èdè ...