Home / Àṣà Oòduà / Ọbásanjọ́ tìkẹ̀kùn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ níbi òkú àna rẹ̀

Ọbásanjọ́ tìkẹ̀kùn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ níbi òkú àna rẹ̀

Ọbásanjọ́ tìkẹ̀kùn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ níbi òkú àna rẹ̀

Ṣé àwọn àgbà bọ̀ wọ́n ní, bí ìṣẹ̀lẹ̀ bá sẹ̀ ní agboolé, a mọ́ ọ kángun sẹ́nìkan ju ẹnìkan lọ.Ọ̀rọ̀ rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí Àárẹ̀ tẹ́lẹ̀rí lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Olusegun Obasanjo ti sọ ìdí tí òun fi ti ìlẹ̀kùn ilé ìjọsìn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ àti ojúlùmọ̀, tó wá sí ibi ayẹyẹ òkú ìyá ìyàwó rẹ̀ ní Ọjọ́ Ẹtì.

Bàbá Ọbásanjọ́ nínú àtẹ̀jáde tó fi léde sọ wí pé, nítorí àrùn Kòrónáfairọ̀ọ̀sì ni òun ṣe gbé ìgbésẹ̀ náà.

Ọbásanjọ́ sàlàyé pé, bí ètò ìsìnkú ọ̀hún ṣe bẹ̀rẹ̀ ní agogo mẹ́wàá Òwúrọ̀ ni ìjọ Saint Peters Anglican Church tó wà ní ọgbà lsara-Remo, ní ìpínlẹ̀ Ògùn, ni òun fúnra òun ti ìlẹ̀kùn ilé ìjọsìn ọ̀hún, kí àwọn ènìyàn má baà ráyè wọlé.

Ó fikún-un pé òun tẹ̀lé àṣẹ ìjọba tó tako ìpéjọpọ̀ àwọn ènìyàn ọlọ́gọ̀ọ̀rọ̀ lásìkò àjàkálẹ̀ àrùn Kofi-19 yìí.

Níṣe ni àwọn òṣìṣẹ́ àti ojúlùmọ̀ náà dúró síta lẹ́yìn ìgbésẹ̀ Bàbá Ọbásanjọ́, tí wọ́n sì lọ sin òkú ọ̀hún lẹ́yìn ìsìn.

Ó kù díẹ̀ kí Màmá Florence Adenekan pé ẹni àádọ̀rún ọdún ló jáde láyé.

Mama Adenekan ni ìyá Bola Ọbásanjọ́ tó jẹ́ ọ̀kan lára ìyàwó Bàbá Ọbásanjọ́.

Ìròyìn gbé e pé ó wà ní Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́ṣì lásìkò ìsìnkú ìyá rẹ̀, tí Bàbá Ọbásanjọ́ sì ṣe ojú rẹ̀ ní ibi ìsìnkú ọ̀hún.

Lẹ́yìn ìsìnkú náà ni Bàbá Ọbásanjọ́ wá tẹ̀síwájú lọ kí àwọn lọ́balọ́ba tó wà ní agbègbè náà.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

Sanwo olu

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré Yínká Àlàbí Ile-iṣẹ Aṣẹ ati Iṣakoso Pajawiri ti Ipinle Eko sọ pe awọn ti setan lati dahun si awọn ipe pajawiri ni ipinlẹ Eko laarin isẹju marun-un pere.Olùdarí Àgbà fún ilé-iṣẹ́ náà, Ọ̀gbẹ́ni Femi Giwa, sọ èyí ní ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan pẹ̀lú awọn oniroyin ní ìlú Èkó.Giwa sọ pé àfojúsùn ilé-iṣẹ́ náà ni láti dín àkókò tó wà láàrín ìyè àti ikú kù nípa rírí dájú pé ìdáhùn náà wáyé láàrín ìṣẹ́jú ...