Home / Àṣà Oòduà / Òṣìṣẹ́ mẹ́rin bọ́ sí gbaga ọlọ́pàá lórí ikú ọ̀gá wọn tó rì sómi

Òṣìṣẹ́ mẹ́rin bọ́ sí gbaga ọlọ́pàá lórí ikú ọ̀gá wọn tó rì sómi

Ìgbákejì Ọ̀gá Àgbà iléeṣẹ́ tó ń rí sí ọ̀rọ̀ owó orí, Price Water Coopers , PwC Nigeria , Tola Ogundipẹ ti jáde láyé.

Ọjọ́ Sátidé ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí ní wá arákùnrin náà lẹ́yìn tó wọ ọkọ̀ ojú omi ní ìpínlẹ̀ Èkó.
Ọjọ́ Àìkú ni wọ́n rí ọkọ̀ ojú omi náà, àmọ́ tí àwọn ọlọ́pàá tó ń ṣiṣẹ́ lórí omi sì rí òkú rẹ̀ ní Ọjọ́ Ajé.

Agbẹnusọ fún iléeṣẹ́ ọlọ́pàá nípìńlẹ̀ Èkó, Muyiwa Adejọbi sọ wí pé, lóòótọ́ ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà wáyé, àwọn òṣìṣẹ́ olóògbé mẹ́rin ni àwọn ti fi ọ̀rọ̀ wá lẹ́nu wò.
Ó sàlàyé wí pé, Kọmíṣọ́nnà ọlọ́pàá nípìńlẹ̀ Èkó, Hakeem Odumosu ti pàṣẹ ìwádìí ìdákọ́ńkọ́ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.

” A ti gbé ìṣẹ̀lẹ̀ náà lọ sí ẹ̀ka tó ń rí sí ọ̀rọ̀ ìwà ọ̀daràn ní Yaba, nípìńlẹ̀ Èkó láti ṣe ìwádìí náà ní kíkún.”

”Tí ìwádìí bá parí, iléeṣẹ́ ọlọ́pàá yóó fi àbájáde hàn sí gbangba.”

Nínú ọ̀rọ̀ tí iléeṣẹ́ Price Waterhouse Coopers fi léde, Ọ̀gá àgbà pátápáta ní Nàìjíríà, Uyi Akpata sàpèjúwe Ogundipẹ tó d’olóògbé náà, gẹ́gẹ́ bí ẹni tó ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀ dójú àmì.

Kó tó di olóògbé, Tola Ogundipe ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí adarí ẹ̀ka “PwC Africa Tax , Assurance Leader for PwC Africa” àti àwọn ipò míràn tó dìmú nínú iléeṣẹ́ PwC.

Iléeṣẹ́’ Price Waterhouse Coopers” ní àwọn yóó fi ọjọ́ ìsìnkú rẹ̀ léde lẹ́yìn ìjíròrò pẹ̀lú àwọn ẹbí àti ará olóògbé náà.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

Alhaja

Ààrẹ Tinubu ti yan Alhaja Ero Arike sí ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ Àwọn Oníròyìn Tuntun tó máa kópa nínú ìpolongo rẹ̀ fún ìdìbò Ààrẹ ọdún 2027.

Ààrẹ Tinubu ti yan Alhaja Ero Arike sí ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ Àwọn Oníròyìn Tuntun(New Media Committee) tó máa kópa nínú ìpolongo rẹ̀ fún ìdìbò Ààrẹ ọdún 2027. Ká ma purọ́, Obìnrin náà ń gbìyànjúTó bá jẹ́ pé ẹni tó bá gbé APC sí orí bíi gala wọ́n ń wá, Alhaja Ero Arike náà ti gbé e sí orí, kó sì fẹ́ràn láti sọ̀kalẹ̀ rárá Ó ti ń ṣe ohun tí ó lè ṣe láti gbé ìjọba àti ẹgbẹ́ APC lárugẹ lórí ...