Home / Àṣà Oòduà / Ọbásanjọ́ tìkẹ̀kùn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ níbi òkú àna rẹ̀

Ọbásanjọ́ tìkẹ̀kùn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ níbi òkú àna rẹ̀

Ọbásanjọ́ tìkẹ̀kùn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ níbi òkú àna rẹ̀

Ṣé àwọn àgbà bọ̀ wọ́n ní, bí ìṣẹ̀lẹ̀ bá sẹ̀ ní agboolé, a mọ́ ọ kángun sẹ́nìkan ju ẹnìkan lọ.Ọ̀rọ̀ rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí Àárẹ̀ tẹ́lẹ̀rí lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Olusegun Obasanjo ti sọ ìdí tí òun fi ti ìlẹ̀kùn ilé ìjọsìn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ àti ojúlùmọ̀, tó wá sí ibi ayẹyẹ òkú ìyá ìyàwó rẹ̀ ní Ọjọ́ Ẹtì.

Bàbá Ọbásanjọ́ nínú àtẹ̀jáde tó fi léde sọ wí pé, nítorí àrùn Kòrónáfairọ̀ọ̀sì ni òun ṣe gbé ìgbésẹ̀ náà.

Ọbásanjọ́ sàlàyé pé, bí ètò ìsìnkú ọ̀hún ṣe bẹ̀rẹ̀ ní agogo mẹ́wàá Òwúrọ̀ ni ìjọ Saint Peters Anglican Church tó wà ní ọgbà lsara-Remo, ní ìpínlẹ̀ Ògùn, ni òun fúnra òun ti ìlẹ̀kùn ilé ìjọsìn ọ̀hún, kí àwọn ènìyàn má baà ráyè wọlé.

Ó fikún-un pé òun tẹ̀lé àṣẹ ìjọba tó tako ìpéjọpọ̀ àwọn ènìyàn ọlọ́gọ̀ọ̀rọ̀ lásìkò àjàkálẹ̀ àrùn Kofi-19 yìí.

Níṣe ni àwọn òṣìṣẹ́ àti ojúlùmọ̀ náà dúró síta lẹ́yìn ìgbésẹ̀ Bàbá Ọbásanjọ́, tí wọ́n sì lọ sin òkú ọ̀hún lẹ́yìn ìsìn.

Ó kù díẹ̀ kí Màmá Florence Adenekan pé ẹni àádọ̀rún ọdún ló jáde láyé.

Mama Adenekan ni ìyá Bola Ọbásanjọ́ tó jẹ́ ọ̀kan lára ìyàwó Bàbá Ọbásanjọ́.

Ìròyìn gbé e pé ó wà ní Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́ṣì lásìkò ìsìnkú ìyá rẹ̀, tí Bàbá Ọbásanjọ́ sì ṣe ojú rẹ̀ ní ibi ìsìnkú ọ̀hún.

Lẹ́yìn ìsìnkú náà ni Bàbá Ọbásanjọ́ wá tẹ̀síwájú lọ kí àwọn lọ́balọ́ba tó wà ní agbègbè náà.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...