Home / Àṣà Oòduà / Ọbásanjọ́ tìkẹ̀kùn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ níbi òkú àna rẹ̀

Ọbásanjọ́ tìkẹ̀kùn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ níbi òkú àna rẹ̀

Ọbásanjọ́ tìkẹ̀kùn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ níbi òkú àna rẹ̀

Ṣé àwọn àgbà bọ̀ wọ́n ní, bí ìṣẹ̀lẹ̀ bá sẹ̀ ní agboolé, a mọ́ ọ kángun sẹ́nìkan ju ẹnìkan lọ.Ọ̀rọ̀ rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí Àárẹ̀ tẹ́lẹ̀rí lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Olusegun Obasanjo ti sọ ìdí tí òun fi ti ìlẹ̀kùn ilé ìjọsìn mọ́ àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ àti ojúlùmọ̀, tó wá sí ibi ayẹyẹ òkú ìyá ìyàwó rẹ̀ ní Ọjọ́ Ẹtì.

Bàbá Ọbásanjọ́ nínú àtẹ̀jáde tó fi léde sọ wí pé, nítorí àrùn Kòrónáfairọ̀ọ̀sì ni òun ṣe gbé ìgbésẹ̀ náà.

Ọbásanjọ́ sàlàyé pé, bí ètò ìsìnkú ọ̀hún ṣe bẹ̀rẹ̀ ní agogo mẹ́wàá Òwúrọ̀ ni ìjọ Saint Peters Anglican Church tó wà ní ọgbà lsara-Remo, ní ìpínlẹ̀ Ògùn, ni òun fúnra òun ti ìlẹ̀kùn ilé ìjọsìn ọ̀hún, kí àwọn ènìyàn má baà ráyè wọlé.

Ó fikún-un pé òun tẹ̀lé àṣẹ ìjọba tó tako ìpéjọpọ̀ àwọn ènìyàn ọlọ́gọ̀ọ̀rọ̀ lásìkò àjàkálẹ̀ àrùn Kofi-19 yìí.

Níṣe ni àwọn òṣìṣẹ́ àti ojúlùmọ̀ náà dúró síta lẹ́yìn ìgbésẹ̀ Bàbá Ọbásanjọ́, tí wọ́n sì lọ sin òkú ọ̀hún lẹ́yìn ìsìn.

Ó kù díẹ̀ kí Màmá Florence Adenekan pé ẹni àádọ̀rún ọdún ló jáde láyé.

Mama Adenekan ni ìyá Bola Ọbásanjọ́ tó jẹ́ ọ̀kan lára ìyàwó Bàbá Ọbásanjọ́.

Ìròyìn gbé e pé ó wà ní Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́ṣì lásìkò ìsìnkú ìyá rẹ̀, tí Bàbá Ọbásanjọ́ sì ṣe ojú rẹ̀ ní ibi ìsìnkú ọ̀hún.

Lẹ́yìn ìsìnkú náà ni Bàbá Ọbásanjọ́ wá tẹ̀síwájú lọ kí àwọn lọ́balọ́ba tó wà ní agbègbè náà.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

Alhaja

Ààrẹ Tinubu ti yan Alhaja Ero Arike sí ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ Àwọn Oníròyìn Tuntun tó máa kópa nínú ìpolongo rẹ̀ fún ìdìbò Ààrẹ ọdún 2027.

Ààrẹ Tinubu ti yan Alhaja Ero Arike sí ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ Àwọn Oníròyìn Tuntun(New Media Committee) tó máa kópa nínú ìpolongo rẹ̀ fún ìdìbò Ààrẹ ọdún 2027. Ká ma purọ́, Obìnrin náà ń gbìyànjúTó bá jẹ́ pé ẹni tó bá gbé APC sí orí bíi gala wọ́n ń wá, Alhaja Ero Arike náà ti gbé e sí orí, kó sì fẹ́ràn láti sọ̀kalẹ̀ rárá Ó ti ń ṣe ohun tí ó lè ṣe láti gbé ìjọba àti ẹgbẹ́ APC lárugẹ lórí ...