Home / Àṣà Oòduà / Àlùfá tọ́ bá ọmọ ọdún méje sùn, wẹ̀wọ̀n ọdún Márùn- ún ní ìpínlẹ̀ Ekiti

Àlùfá tọ́ bá ọmọ ọdún méje sùn, wẹ̀wọ̀n ọdún Márùn- ún ní ìpínlẹ̀ Ekiti

Ọjọ́ gbogbo n t’olè, ọjọ́ kan n t’olóhun.
Ìjọba ìpínlẹ̀ Ekiti tífìtàn balẹ̀ bí wọ́n ṣe jẹ́ ìpínlẹ̀ àkọ́kọ́ tí yóò bẹ̀rẹ̀ láti máa dárúkọ ọ̀daràn afipá bánilòpọ̀ hàn àti láti máa dójú tì wọ́n.

Gómìnà ìpínlẹ̀ náà Kayode Fayemi gbé e jáde lójú òpó twitter rẹ̀ pé àsìkò ti tó láti máa fi ojú aṣebi hàn lásìkò tó gbé àwòrán ẹni ọ̀wọ̀ Asateru Gabriel ti ìjọ St Andrew Anglican Ifinsin -Ekiti nígbà kan.

Gabriel ti fọjú ba ilé ẹjọ ó si jẹ̀bi ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan, nítori ìdí èyí yóò maa ṣẹ̀wọ̀n ọdún márùn ní ọgbà ẹ̀wọ̀n Ìjọba ní Ado Ekiti fún ẹ̀sùn ìfipá bá ọmọ ọdún méje lòpọ̀.

Ní bayiì orúkọ rẹ̀ ti wọ ìwé àkọsílẹ̀ àwọn olùfipábánilòpọ̀ ní ilé ìṣẹ́ ìdajọ́.

Èyí jẹ́ ìpínlẹ̀ Gúúsù- ìwọ̀ -oòrùn àkọ́kọ́ tí yóò gbé ìgbesẹ̀ yìí.

Fẹ́mi Akínṣọlá
Iroyinowuro

About ayangalu

x

Check Also

Sanwo olu

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré Yínká Àlàbí Ile-iṣẹ Aṣẹ ati Iṣakoso Pajawiri ti Ipinle Eko sọ pe awọn ti setan lati dahun si awọn ipe pajawiri ni ipinlẹ Eko laarin isẹju marun-un pere.Olùdarí Àgbà fún ilé-iṣẹ́ náà, Ọ̀gbẹ́ni Femi Giwa, sọ èyí ní ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan pẹ̀lú awọn oniroyin ní ìlú Èkó.Giwa sọ pé àfojúsùn ilé-iṣẹ́ náà ni láti dín àkókò tó wà láàrín ìyè àti ikú kù nípa rírí dájú pé ìdáhùn náà wáyé láàrín ìṣẹ́jú ...