Home / Àṣà Oòduà / APC kò ní ì ṣe ìdìbò ní ìpínlẹ̀ Òǹdó àyàfi.. Olùdíje kan

APC kò ní ì ṣe ìdìbò ní ìpínlẹ̀ Òǹdó àyàfi.. Olùdíje kan


APC kò ní ì ṣe ìdìbò ní ìpínlẹ̀ Òǹdó àyàfi.. Olùdíje kan

Láìpẹ́ yìí ni ìròyìn kàn pé ìgbìmọ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressive Congress (APC) tó ń ṣe àyẹ̀wò àwọn olùdíje lábẹ́ ẹgbẹ́ náà sọ pé Segun Abraham ni kò kójó òṣùwọ̀n tó nínú àwọn tó ń díje nítori náà ni won ṣe yọ.

Segun Abraham jẹ́ ọ̀kan lára àwọn méjìlá tó ń dije lábẹ́ àsíá ẹgbẹ́ APC tó sì ti gbá ìwé láti fi èrò rẹ̀ hàn pé, òun ṣetan láti kópa nínú ìdìbò abẹ́lé ẹgbẹ́ náà ti yóò wáye ní Ogúnjọ́, Oṣù Keje ọdún yìí.

Sùgbọ́n nínú ìfọ̀rọ̀wáni lẹ́nu wò tí akọròyìn ṣe fún olùdíje náà, Ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé títí di àsìkò yìí, ìgbìmọ̀ kò ti fi tó òun léti pé òun ni wọ́n yọ.

Títí di àsìkò yìí mí ò ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìgbìmọ̀ àyẹ̀wò pé èmì ni wọ́n yọ, tàbi ki wọ́n kọ lẹta nípa rẹ, wọ́n ni, wọ́n ni, ní mò ń gbọ́.”

Àwọn tí wọ́n jọ díje ni Joseph Olusola Iji, Odimayo Okunjimi, Olayide Owolabi Adelami, Isaacs Duerimini Kekemeke, Olusola Oke Alex, lfeoluwa Olusola Oyedele àti Olajumoke Olubusola Anifowoshe.

Àwọn tó kù ni Awodeyi Akinsehinwa Akinola Colinus, Olubukola Adetula, Dr. Abraham Olusegun Michael, Gomina Rotimi Akeredolu ati Dokita Nathaniel Adojutelegan.

http://iroyinowuro.com.ng/2020/07/16/apc-ko-ni-i-%e1%b9%a3e-idibo-ni-ipinle-o%c7%b9do-ayafi-oludije-kan/

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

Sanwo olu

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré Yínká Àlàbí Ile-iṣẹ Aṣẹ ati Iṣakoso Pajawiri ti Ipinle Eko sọ pe awọn ti setan lati dahun si awọn ipe pajawiri ni ipinlẹ Eko laarin isẹju marun-un pere.Olùdarí Àgbà fún ilé-iṣẹ́ náà, Ọ̀gbẹ́ni Femi Giwa, sọ èyí ní ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan pẹ̀lú awọn oniroyin ní ìlú Èkó.Giwa sọ pé àfojúsùn ilé-iṣẹ́ náà ni láti dín àkókò tó wà láàrín ìyè àti ikú kù nípa rírí dájú pé ìdáhùn náà wáyé láàrín ìṣẹ́jú ...