Home / Àṣà Oòduà / Àwo̩n aké̩kò̩ó̩ máa wo̩lé láìpé̩

Àwo̩n aké̩kò̩ó̩ máa wo̩lé láìpé̩

Àwo̩n aké̩kò̩ó̩ máa wo̩lé láìpé̩

Gbogbo igbiyanju ni awon ajo eto eko ti wa ninu awon ajo NCDC n se bayii lati le je ki awon akekoo wole eko won.


Oro arun coronavirus yii ti su gbogbo aye. Ile ti su awon akekoo, awon ile-iwe aladaani n gbiyanju eto eko ori ayelujara, bi o tile je pe “oju apa ko jo oju ara”. Eto eko oju ofurufu ko rorun bii ti ojukoju.


Bi awon akekoo se n saroye pe eto eko naa ko da bii ki awon ri akegbe awon ni awon oluko naa ni “ki owo ma dile lasan ni”.


Awon oluko kan tile ni awon ise kan ko tile see fi ogbon ko rara loju ofurufu, awon ise bii aworan yiya, ina dida, abala isiro Kan ati gbogbo ise to nilo ki awon akekoo dan wo loju oluko.


Awon obi gan-an n saroye nipa ohun ti eto eko ayelujara naa n gbe lo lapo won nipa data rira, epo petiro ati awon nnkan miiran. Awon obi ni bee ni ko si owo lowo.


Eyi to tun wa dun awon oloju aanu ju ni awon akekoo ile iwe ijoba ti ko si anfaani foonu tabi komputa fun rara.


Eyi naa mumu laye ijoba apapo nitori opo awon oluko ile-iwe aladaani ni won je, ko sise, ko sowo fun. Ipade osan ati oru ti n lo lati wo bi awon Kan se maa lo ile-iwe ni aaro ti awon Kan maa lo losan lati le din ero ku die.

Ìròyìn láti o̩wó̩ Yínká Àlàbí

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...