Home / Àṣà Oòduà / Èsì àyẹ̀wò tuntun Nàìjíríà fihàn pé “313” èèyàn ti gbàlejò Kofi 19 …àjọ NCDC

Èsì àyẹ̀wò tuntun Nàìjíríà fihàn pé “313” èèyàn ti gbàlejò Kofi 19 …àjọ NCDC

Èsì àyẹ̀wò tuntun Nàìjíríà fihàn pé “313” èèyàn ti gbàlejò Kofi 19 …àjọ NCDC

À fi kí á bẹ Ọlọ́run kó bá wa dásí ọ̀rọ̀ àjàkálẹ̀ àrùn ajániláyà pàtì yìí, bí àwọn tó ní kòrónáfairọ̀ọ̀sì ní Nàìjíríà ti ń peléke sí i báyìí,lẹ́yìn tí àjọ NCDC tún kéde okòólélọ́ọ̀dúnrún dín méje èèyàn tí èsì àyẹ̀wò wọn sẹ̀sẹ̀ jáde.

Ní báyìí, èèyàn ẹgbẹ̀rún méje, àti . òjìlélẹ́gbẹ̀rin dínkan (7839) ni àkọsílẹ̀ wà pé ó ti ní àrùn náà ní Nàìjíríà.

Àkójọpọ̀ àwọn ìpínlẹ̀ tí èsì tuntun náà ti wá nìyí.

Àjọ tó ń mójútó àjàkálẹ̀ arun l’órílẹ̀èdè Nàìjíríà, NCDC, kéde pé ènìyàn igba àti márùndínláádọ́rin ni àyẹ̀wò fihàn pé ó tún ní àrùn ni apinni léèmí Kòrónáfairọ̀ọ̀sì Naijiria.

Nínú èsì àyẹ̀wò náà, ìpínlẹ̀ Èkó ní èèyàn mẹ́taleláàdóje, Ọ̀yọ́ ní mẹtàlélọ́gbọ̀n, Edo sì ní méjìdínlọ́gọbn.

àwọn tó ti ní l’órílẹ̀èdè Nàìjíríà jẹ́ ẹgbẹ̀rún méje, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́rìndinlọ́ggbọ̀n (7526).

Ẹgbẹ̀rún méjì àti mẹ́rìnléláàdọ́sàn (2174), ti rí ìwòsàn, okòólérúgba lé kan (221) sì ti kú.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...