Home / Àṣà Oòduà / Ìjọba Àpapọ̀ Kò Gbẹ́sẹ̀lẹ̀ Lé Owó Tó Tọ́ Sáwọn Ìjọba Ìbílẹ̀ L‘ọyọ

Ìjọba Àpapọ̀ Kò Gbẹ́sẹ̀lẹ̀ Lé Owó Tó Tọ́ Sáwọn Ìjọba Ìbílẹ̀ L‘ọyọ

Ìjọba àpapọ̀ kò gbẹ́sẹ̀lẹ̀ lé owó tó tọ́ sáwọn ìjọba ìbílẹ̀ l‘Ọyọ

Fẹ́mi Akínṣọlá

Lórí ọ̀rọ̀ kan tó gbà gboro kan pé àgbẹjọrò àgbà orilẹ̀-èdè Naijiria, Abubakar Malami ti pàṣẹ fún gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo láti gba àwọn alága káńṣù ti wọ́n yọ nípò pada, Ìjọba Ọyọ ti fèsì lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.

Nígbà tó ń sẹ̀rí ọ̀rọ̀ náà, Akọ̀wé ìkéde ìjọba ìpińlẹ̀ Oyo, Ọgbẹ́ni Taiwo Adisa ní, ìrọ tó jìnà sí òtítọ ni nítori pé òun kò tí ì rí lẹ́ta kankan tó jọ bẹ́ẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Malami.
Ó fí kún un pé kò sí ìgbà kankan tí Malami jáde láti sọ pé òun kọ lẹ́tà ránṣẹ́ si ìpínlẹ̀ Oyo, pẹ̀lú àfikún pé, ó se pàtàki ki àwọn akọ̀ròyìn máa ṣe ìwádìí wọ́n dáradára, ki wọ́n tó máa tan ìròyìn tí kò fi ìdí múlẹ̀ káàkiri.

Lórí àhesọ ọ̀rọ̀ kan tó sọ pé, ìjọba ìpinlẹ̀ Oyo kò rí owó gbà láti ọ̀dọ̀ ìjọba àpapọ̀ fún àwọn ìjọba ìbilẹ̀, nítori pé àwọn Alága fìdíẹ ni wọ́n fi sí ìjọba Káńsù Adisa ní òfo ọjọ́ kejì ọjà ni ọ̀rọ̀ ọ̀hún.

” Ẹni tí wọ́n bá nà ló yẹ kí ara máa ta, tí ìjọba ìpínlẹ̀ Ọyọ kò bá rí owó gbà, ẹnu ìjọba ìpínlẹ̀ ni ẹ ó ti gbọ́ kìí ṣe ẹnu àwọn ìròyìn ẹlẹ́jẹ̀. Nítorí náà, òfúùtù fẹ́ẹ̀tẹ̀ ni Ìròyìn tó ní àwọn Ìjọba ìbílẹ̀ ní Ọyọ kò rí owó tó tọ́ sí wọn gbà láti ọ̀dọ̀ Ìjọba àpapọ̀.”

About ayangalu

x

Check Also

Sanwo olu

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré Yínká Àlàbí Ile-iṣẹ Aṣẹ ati Iṣakoso Pajawiri ti Ipinle Eko sọ pe awọn ti setan lati dahun si awọn ipe pajawiri ni ipinlẹ Eko laarin isẹju marun-un pere.Olùdarí Àgbà fún ilé-iṣẹ́ náà, Ọ̀gbẹ́ni Femi Giwa, sọ èyí ní ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan pẹ̀lú awọn oniroyin ní ìlú Èkó.Giwa sọ pé àfojúsùn ilé-iṣẹ́ náà ni láti dín àkókò tó wà láàrín ìyè àti ikú kù nípa rírí dájú pé ìdáhùn náà wáyé láàrín ìṣẹ́jú ...