Home / Àṣà Oòduà / Maryam Sanda ṣì wà lẹ́wọ̀n, Buhari kò dáa sílẹ̀.

Maryam Sanda ṣì wà lẹ́wọ̀n, Buhari kò dáa sílẹ̀.

Iléeṣẹ́ Ààrẹ ló sọ pé Ìròyìn tó ń jà rànyìnrànyìn kiri pé Ààrẹ Muhammadu Buhari tí darí jin arábìnrin náà kìí ṣe òtítọ́ rárá.Ki àwọn èèyàn kọtí ọ̀gbọin sí i.
Ní oṣù kínní ọdún yìí ni ilé ẹjọ́ dá arábìnrin Maryam Sanda lẹ́bi ikú pé ó jẹ̀bi ẹ̀sùn gígún ọkọ rẹ̀ pa tí wọ́n fi kàn án.

Amúgbálẹ́ẹ̀gbẹ́ fún Ààrẹ Buhari lórí ọ̀rọ̀ Ìròyìn ayélujára, Bashir Ahmad ló fi síta lójú òpó twitter rẹ̀ pé, ara ọ̀nà láti ba orúkọ rere tí Ààrẹ ti ní lórí ètò ìdáríjì fáwọn ẹlẹ́wọ́n tó wáyé láìpẹ́ yìí lọ́nà àti mú àdínkù bá àwọn ọgbà ẹ̀wọ̀n tó kún fọ́fọ́ lórílẹ̀-èdè yìí.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

tirela

Tírélà jábọ́ láti orí afárá l’Eko, rún Korope méji pa

Tírélà jábọ́ láti orí afárá l’Eko, rún Korope méji pa Fẹ́mi Akínṣọlá Aago mẹ́sàn-án òwúrọ̀ ló ń lọ lu lọjọ Àbámẹ́ta, ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọ̀n, oṣù Kerin 2025, tírélà kan fi jábọ́ láti orí afárá Pen Cinema, Agege, l’Ekoo, tó sì run ọkọ̀ Kórópe méjì tó jábọ́ lé lórí pa. Ajọ Lagos State Traffic Management Authority (LASTMA), to n ri si igbokegbodo ọkọ l’Ekoo, fidi iṣẹlẹ yii mulẹ. Atẹjade kan ti Adari iṣẹlẹ bi eyi ati ilaniloye ni LASTMA, Adebayo Taofiq, fi ...