Home / Àṣà Oòduà / Maryam Sanda ṣì wà lẹ́wọ̀n, Buhari kò dáa sílẹ̀.

Maryam Sanda ṣì wà lẹ́wọ̀n, Buhari kò dáa sílẹ̀.

Iléeṣẹ́ Ààrẹ ló sọ pé Ìròyìn tó ń jà rànyìnrànyìn kiri pé Ààrẹ Muhammadu Buhari tí darí jin arábìnrin náà kìí ṣe òtítọ́ rárá.Ki àwọn èèyàn kọtí ọ̀gbọin sí i.
Ní oṣù kínní ọdún yìí ni ilé ẹjọ́ dá arábìnrin Maryam Sanda lẹ́bi ikú pé ó jẹ̀bi ẹ̀sùn gígún ọkọ rẹ̀ pa tí wọ́n fi kàn án.

Amúgbálẹ́ẹ̀gbẹ́ fún Ààrẹ Buhari lórí ọ̀rọ̀ Ìròyìn ayélujára, Bashir Ahmad ló fi síta lójú òpó twitter rẹ̀ pé, ara ọ̀nà láti ba orúkọ rere tí Ààrẹ ti ní lórí ètò ìdáríjì fáwọn ẹlẹ́wọ́n tó wáyé láìpẹ́ yìí lọ́nà àti mú àdínkù bá àwọn ọgbà ẹ̀wọ̀n tó kún fọ́fọ́ lórílẹ̀-èdè yìí.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

Alhaja

Ààrẹ Tinubu ti yan Alhaja Ero Arike sí ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ Àwọn Oníròyìn Tuntun tó máa kópa nínú ìpolongo rẹ̀ fún ìdìbò Ààrẹ ọdún 2027.

Ààrẹ Tinubu ti yan Alhaja Ero Arike sí ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ Àwọn Oníròyìn Tuntun(New Media Committee) tó máa kópa nínú ìpolongo rẹ̀ fún ìdìbò Ààrẹ ọdún 2027. Ká ma purọ́, Obìnrin náà ń gbìyànjúTó bá jẹ́ pé ẹni tó bá gbé APC sí orí bíi gala wọ́n ń wá, Alhaja Ero Arike náà ti gbé e sí orí, kó sì fẹ́ràn láti sọ̀kalẹ̀ rárá Ó ti ń ṣe ohun tí ó lè ṣe láti gbé ìjọba àti ẹgbẹ́ APC lárugẹ lórí ...