Home / Àṣà Oòduà / Àdúrà làsìkò yí gbà pẹ̀lú ìfaradà láti ṣẹ́gun àrùn apinni léèmí Coronavirus–Ààrẹ Buhari

Àdúrà làsìkò yí gbà pẹ̀lú ìfaradà láti ṣẹ́gun àrùn apinni léèmí Coronavirus–Ààrẹ Buhari

Ààrẹ Buhari kí àwọn ọmọ Nàìjíríà kú àfaradà bí gbogbo nǹkan ṣe ń lọ lásìkò Coronavirus yìí

Nínú ọ̀rọ̀ ìkínni kú ọdún Àjíǹde tó fi ṣọwọ́ sáwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà

Ààrẹ Buhari ṣàlàyé pé ìgbáyégbádùn àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kìí ṣé oun tó ṣe é dúnàádúrà lé lórí ṣùgbọ́n ìgbésẹ̀ ààbò àti àlàáfíà aráàlú ṣe kókó.
Ààrẹ fi kún un pé, ó wu òun kí wọ́n jáde ṣọdún Àjíǹde, ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Covid 19 yìí ń gbẹ́mìí kúkúrú gígùn, o sì jẹ́ ohun ìbànújẹ́.
Ààrẹ wá fikún un pé,ki àwọn ènìyàn o tẹ̀lé òfin kónílé-ó-gbélé tí Ìjọba ti pàṣẹ kónílé-ó-gbélé o.

Àdúrà làsìkò yí gbà pẹ̀lú ìfaradà láti ṣẹ́gun àrùn apinni léèmí Coronavirus–Ààrẹ Buhari

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

seun kuti

Orí kó Seun Kuti yọ kúrò lọ́wọ́ ikú ní yàrá ìgbàlejò US

Mary Fágbohùn Olórin Afrobeat Seun Kuti ti fi ìrírí ibanuje ọkàn rẹ̀ ní orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà han nígbà tí ọta ibọn kan gúnlẹ̀ lójú fèrèsé yàrá igbalejo rẹ̀. O salaye ibapade to ba ni lẹru naa lori oju-iwe Instagram rẹ, o fi fidio ferese ti ọta ibọn naa bajẹ ati iho re han. Seun, ẹni ti o ṣalaye iyalẹnu, beere iwoye ti aabo ni Amẹrika. Ninu fonran naa, Seun Kuti sọ pe oun wa ninu yara igbalejo, ti oun n sinmi, ...