Home / Àṣà Oòduà / Adarí àgbà ilé ìwòsàn UCH kò ní àrùn Coronavirus mọ́

Adarí àgbà ilé ìwòsàn UCH kò ní àrùn Coronavirus mọ́

Họ́wùú! bí babaláwo bá ń kígbe ẹ̀fọ́rí, kín ni yóó jẹ́ àtubọtán aláìsàn? Kò jẹ́ jẹ́ bẹ́ẹ̀.

Adarí àgbà ilé ìwòsàn ẹ̀kọ́ṣẹ́, UCH Íbàdàn Ọ̀jọ̀gbọ́n Abiodun Otegbayo ti yiijẹ o, kò ní àrùn Coronavirus mọ́ lẹ́yìn tó sàyẹ̀wò àrùn náà nígbà kejì.

Ṣaájú ní Otegbayo ti kọ́ sàyẹ̀wò, tí èsì àyẹ̀wò ọ̀hún sì fi hàn pé ó ti fara káásá àrùn náà, èyí tó mú kó ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ fún ìtọ́jú.

Ṣùgbọ́n lẹ́yìn tó lo ọjọ́ mẹ́jọ ní ìyàsọ́tọ̀ ọ̀hún ló sàyẹ̀wò lẹ́ẹ̀kejì, tí èsì sì fi hàn pé kò ní àrùn náà lára mọ́.

Agbẹnusọ ilé ìwòsàn ẹ̀kọ́ṣẹ́ UCH, Toye Akinrinlola ló fi ọ̀rọ̀ náà léde fún àwọn akọ̀rọ̀yìn lọ́jọ́bọ

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

ojo keji

Ó San Owó Ilé Ìwé Mi Títí Mo Fi Jáde, Ṣùgbọ́n Mo Fi Májèlé San!

Àti ilé ìwé e gírámà ni èmi àti Kọ́lá ti jọ ń fẹ́ ra wa. Àwọn òbí i mi ò kí ń fẹ́ rí Kọ́lá pẹ̀lú u mi nítorí ààfín ni. Nígbà tí mo fẹ́ wo ile ìwé gíga ni bàbá à mi ní àìsàn an rọ́pá, rọsẹ̀,ọpẹ́lọpẹ́ kọ́lá tó san owó ilé ìwé è mi láti ìgbà tí mo wolé ẹ̀kọ́ gíga títí mo fi jádé. Nígbà ti mo lọ ṣe agùnbánirọ̀ mo pàdé sẹ́nátọ kán,èmi àti ẹ̀ sì ...