Home / Àṣà Oòduà / Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn wọ́gilé ìyọnípò Oshiomole gẹ́gẹ́ bíi alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC

Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn wọ́gilé ìyọnípò Oshiomole gẹ́gẹ́ bíi alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC

Ọ̀rọ̀ fini lògbòlògbò yini nù lọ̀rọ̀ ọ Alága gbogbo gbòò ẹgbẹ́ òsèlú APC dà báyìí o, bí Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn ìlú Abuja ti ní Adams Oshiomhole sì ni Alága gbogbo gbòò fún ẹgbẹ́ òṣèlú APC.

Ìgbìmọ̀ ẹlẹ́ni mẹ́ta tó ń gbọ́ ẹjọ́ náà, tí adájọ́ Abubaka Datti Yahaya kó sòdí wọ́gilé ẹjọ́ tí ilé ẹjọ́ gíga ìlú Abuja dá Ṣaájú, léyìí tó yọ Oshiomole nípò gẹ́gẹ́ bí Alága ẹgbẹ́ ọ̀hún.

Ṣaájú ni oshiomole ti rọ ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn náà láti gbé ìdájọ́ ìyọnípò rẹ̀ náà tì ṣí ẹ̀gbẹ́ kan.

Nígbà tó ń gbé ìdájọ́ rẹ̀ kalẹ̀, adájọ́ náà kìlọ̀ fún àwọn tí ọ̀rọ̀ ọ̀hún kàn láti má gbé ìgbésẹ̀ tí yóó tako ìdájọ́ tó gbé kalẹ̀.

Lẹ́yìn náà ló rọ àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú láti máa yanjú aáwọ̀ tó bá wà láàrin wọn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìyá dípò kí wọ́n máa yọ ilé ẹjọ́ lẹ́nu.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...