Home / Àṣà Oòduà / Orí kó ènìyàn márùn-ún yọ lọ́wọ́ coronavirus l’Ekoo

Orí kó ènìyàn márùn-ún yọ lọ́wọ́ coronavirus l’Ekoo

Orí kó ènìyàn márùn-ún yọ lọ́wọ́ coronavirus l’Ekoo
Ìròyìn láti ọwọ́ Yínká Àlàbí

Alaisan marun-un ninu awon ti arun buruku covid-19 ti n ba finra lati bii ose meloo kan seyin gba idande. Yoruba bo “won ni alaare ko ki n ra si inu yara, bi o segun aisan, yoo fi ese ara re rin jade, bi o ba si yiwo naa, won a gbe oku re jade”.

Eyi lo sele si awon marun-un ti arun coronavirus ti n ba poo, ti won si segun arun naa, nitori pe gbogbo ayewo ti won se fun won lera-lera si gbee pe aisan naa ko si lara won mo.

Minisita eto ilera Dokita Osagie Ehanire ati ajo NCDC se tun n parowo si gbogbo omo Naijiria, won ni arun naa ko tii ni oogun kan gbogi nipa idi eyi, ki awon eniyan so ewe agbeje mowo. Ki onikaluku si gbe inu ile re gege bi gbogbo eka ijoba se n forere.

http://iroyinowuro.com.ng/2020/03/30/ori-ko-eniyan-marun-un-yo-lowo-coronavirus-lekoo/

About ayangalu

x

Check Also

Sanwo olu

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré

Ìpínlẹ̀ Eko ní ìfojúsùn ìpè pàjáwìrì ìsẹ́jú márùn-ún péré Yínká Àlàbí Ile-iṣẹ Aṣẹ ati Iṣakoso Pajawiri ti Ipinle Eko sọ pe awọn ti setan lati dahun si awọn ipe pajawiri ni ipinlẹ Eko laarin isẹju marun-un pere.Olùdarí Àgbà fún ilé-iṣẹ́ náà, Ọ̀gbẹ́ni Femi Giwa, sọ èyí ní ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan pẹ̀lú awọn oniroyin ní ìlú Èkó.Giwa sọ pé àfojúsùn ilé-iṣẹ́ náà ni láti dín àkókò tó wà láàrín ìyè àti ikú kù nípa rírí dájú pé ìdáhùn náà wáyé láàrín ìṣẹ́jú ...