Home / Àṣà Oòduà / Èèyàn 627 ló lùgbàdì àrùn Coronavirus ní Naijiria ní Ọjọ́ Ẹtì

Èèyàn 627 ló lùgbàdì àrùn Coronavirus ní Naijiria ní Ọjọ́ Ẹtì

Èèyàn 627 ló lùgbàdì àrùn Coronavirus ní Naijiria ní Ọjọ́ Ẹtì

Ẹgbẹ̀ta lé lọ́gbọ̀n o dín mẹta èèyàn (627 )tuntun míì ló ṣẹ̀sẹ̀ lùgbàdi àrùn Kofi -19 ní Nàìjíríà.

Àjọ tó ń rí sí ìdènà àti amójútó àjàkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Kòrónáfairọ̀ọ̀sì, NCDC ló fi ìkéde náà síta lójú òpó abẹ́yefò Twitter rẹ̀.

Àpapọ̀ àwọn tó ti ní àrùn náà káàkiri orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti wá di 15,181 báyìí.

Èèyàn 4,891 ló ti rí ìwòsàn gbà, nígbà tí àwọn 399 ti dèrò ọ̀run nípaṣẹ̀ àrùn ajániláyà pàtì méèmí ẹni lọ ọ̀hún.

Iye àwọn èèyàn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ kó àrùn náà ní ìpínlẹ̀ kọ̀ọ̀kan rèé:

Eko-229,FCT-65

Abia-54,Borno-42

Oyo-35,Rivers-28

Edo-28,Gombe-27

Ogun-21,Plateau-18

Delta-18,Bauchi-10

Kaduna-10,Benue-9

Ondo-8,Kwara-6

Nasarawa-4,Enugu-4

Sokoto-3,Niger-3

Kebbi-3,Yobe-1,Kano-1

Ìjọba lẹ́lẹ́kaǹka ń pàrọwà sí àwọn ọmọ Orílẹ̀ yìí láti ríi pé àdínkù bá ìtànkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Kofi-19.

Bí ariwo ìkéde ṣé n lọ yìí, síbẹ̀ àwọn èèyàn kan nílẹ̀ yìí sí n yínmú pé irọ́ ni kò sí àrùn náà, àti pé, bí ó bá wà, ó yẹ kí wọ́n máa ṣàfíhàn àwọn èèyàn náà fún àwọn wò bíìran.
Ẹni ikú pa kò tó nǹkan, ẹni àìgbọ́n pa ló pọ̀.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

Alhaja

Ààrẹ Tinubu ti yan Alhaja Ero Arike sí ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ Àwọn Oníròyìn Tuntun tó máa kópa nínú ìpolongo rẹ̀ fún ìdìbò Ààrẹ ọdún 2027.

Ààrẹ Tinubu ti yan Alhaja Ero Arike sí ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ Àwọn Oníròyìn Tuntun(New Media Committee) tó máa kópa nínú ìpolongo rẹ̀ fún ìdìbò Ààrẹ ọdún 2027. Ká ma purọ́, Obìnrin náà ń gbìyànjúTó bá jẹ́ pé ẹni tó bá gbé APC sí orí bíi gala wọ́n ń wá, Alhaja Ero Arike náà ti gbé e sí orí, kó sì fẹ́ràn láti sọ̀kalẹ̀ rárá Ó ti ń ṣe ohun tí ó lè ṣe láti gbé ìjọba àti ẹgbẹ́ APC lárugẹ lórí ...