Home / Àṣà Oòduà / Orisirisi: Àwọn àǹjàǹnú ń gbowó oṣù l’ájọ Sùbẹ́ẹ̀bù Kwara- EFCC

Orisirisi: Àwọn àǹjàǹnú ń gbowó oṣù l’ájọ Sùbẹ́ẹ̀bù Kwara- EFCC

Àwọn àǹjàǹnú ń gbowó oṣù l’ájọ Sùbẹ́ẹ̀bù Kwara- EFCC

Àjọ tó ń gbógun ti ìwà jẹgúdújẹrá lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà EFCC sọ pé àṣírí àwọn ayédèrú òṣìṣẹ́ ẹgbẹ̀rún kan àjọ tó ń ṣàkóso ètò ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ nípìńlẹ̀ Kwara ti tú sí àwọn lọ́wọ́.

Orúkọ àwọn ayédèrú òṣìṣẹ́ yìí làwọn kan gb’ọ̀nà ẹ̀bùrú fi sínú orúkọ àwọn tó ń ṣiṣẹ́ tí wọ́n sì ń lu owó oṣù wọn ní póńpó.

Olórí àjọ náà tó ń bójú tó ẹ̀ka ìpínlẹ̀ Kwara ló fi ọ̀rọ̀ yìí tó àwọn oníròyìn létí nílù Ilọrin lọ́jọ́bọ.

Ọ̀gbẹ́ni Isyaku Sharu sọ pé nínú àwọn tí àwọn mú láti wá wí tẹnu wọn lórí ọ̀rọ̀ yìí ni Akọ̀wé àgbà kan àti Olùdarí iléeṣẹ́ Ìjọba lábẹ́ Ìjọba ìpínlẹ̀ Kwara kan náà wà.

Lójú òpó abẹ́yefò Twitter Efcc bákan náà ni wọ́n fi síbẹ̀ pé, àwọn ti rí owó tó tó mílíọ̀nù méjìdínlógóje náírà gbà padà lọ́wọ́ àwọn tó ku owó ọba ní póńpó.

Ó tún fikún ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé àwọn tí ṣaájú dá àwọn owó kan t’áwọn rí gbà padà fún Gómìnà Kwara, Abdulrahman Abdurazaq

Àjọ Sùbẹ́ẹ̀bù ló yẹ kí ó má mójútó ọ̀rọ̀ ètò ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ní Kwara ṣùgbọ́n, ẹnu kò sìn lẹ́yìn àjọ náà pẹ̀lú bí àwọn olùkọ́ kò se rí owó oṣù gbà déédé, tí àwọn ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ kò sì wà nípò to wú ni lórí.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...