Home / Àṣà Oòduà / È̩yin òsìsé̩ mi nílò àyè̩wò coronavirus kíákíá- Akeredolu

È̩yin òsìsé̩ mi nílò àyè̩wò coronavirus kíákíá- Akeredolu

È̩yin òsìsé̩ mi nílò àyè̩wò coronavirus kíákíá – Akeredolu

Arakunrin Rotimi Akeredolu ti o je gomina ipinle Ondo lo n gba awon alabasise re niyanju ki won fi oro ti oun se arikogbon.


O ni iba lasan ni o se oun ti oun si se itoju ara laarin ojo meji pere. O ni leyin re ni awon ore gba oun nimoran lati se ayewo ajakale arun coronavirus.


Gomina naa ni “iyan jija lo n ba ore je” oun se ayewo ti esi ayewo si gbe pe oun ti ko arun naa.


O ni tii di asiko yii, oun ko tii le so ibi ti ati ona ti oun gba ko aisan naa. Alagba Akeredolu salaye yii funra re lori afefe pe ki won wo oun pe saka ni ara da.

Oun ko tile ni inira kankan ni eyi ti awon onimo oyinbo ni ohun lo dara ju. Won ni ti eniyan ba tete kefin arun yii ti o si tete gbogun tii lo dara ju ki o to wo ara.


Eyi lo mu ki gomina gba awon osise re niyanju pe ki won tete lo se ayewo ara won nipa arun naa ki eni to ba nii le tete gbogun tii.

Yínká Àlàbí

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...