Home / Àṣà Oòduà / Èèyàn 627 ló lùgbàdì àrùn Coronavirus ní Naijiria ní Ọjọ́ Ẹtì

Èèyàn 627 ló lùgbàdì àrùn Coronavirus ní Naijiria ní Ọjọ́ Ẹtì

Èèyàn 627 ló lùgbàdì àrùn Coronavirus ní Naijiria ní Ọjọ́ Ẹtì

Ẹgbẹ̀ta lé lọ́gbọ̀n o dín mẹta èèyàn (627 )tuntun míì ló ṣẹ̀sẹ̀ lùgbàdi àrùn Kofi -19 ní Nàìjíríà.

Àjọ tó ń rí sí ìdènà àti amójútó àjàkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Kòrónáfairọ̀ọ̀sì, NCDC ló fi ìkéde náà síta lójú òpó abẹ́yefò Twitter rẹ̀.

Àpapọ̀ àwọn tó ti ní àrùn náà káàkiri orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti wá di 15,181 báyìí.

Èèyàn 4,891 ló ti rí ìwòsàn gbà, nígbà tí àwọn 399 ti dèrò ọ̀run nípaṣẹ̀ àrùn ajániláyà pàtì méèmí ẹni lọ ọ̀hún.

Iye àwọn èèyàn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ kó àrùn náà ní ìpínlẹ̀ kọ̀ọ̀kan rèé:

Eko-229,FCT-65

Abia-54,Borno-42

Oyo-35,Rivers-28

Edo-28,Gombe-27

Ogun-21,Plateau-18

Delta-18,Bauchi-10

Kaduna-10,Benue-9

Ondo-8,Kwara-6

Nasarawa-4,Enugu-4

Sokoto-3,Niger-3

Kebbi-3,Yobe-1,Kano-1

Ìjọba lẹ́lẹ́kaǹka ń pàrọwà sí àwọn ọmọ Orílẹ̀ yìí láti ríi pé àdínkù bá ìtànkálẹ̀ àrùn apinni léèmí Kofi-19.

Bí ariwo ìkéde ṣé n lọ yìí, síbẹ̀ àwọn èèyàn kan nílẹ̀ yìí sí n yínmú pé irọ́ ni kò sí àrùn náà, àti pé, bí ó bá wà, ó yẹ kí wọ́n máa ṣàfíhàn àwọn èèyàn náà fún àwọn wò bíìran.
Ẹni ikú pa kò tó nǹkan, ẹni àìgbọ́n pa ló pọ̀.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...