Home / Àṣà Oòduà / Ẹgbẹ ́Afẹ́nifẹ́re kọminú lórí ìwádìí ikú ọmọ Baba Faṣọranti to jẹ olori Afẹ́nifẹ́re – Odumakin

Ẹgbẹ ́Afẹ́nifẹ́re kọminú lórí ìwádìí ikú ọmọ Baba Faṣọranti to jẹ olori Afẹ́nifẹ́re – Odumakin

Ẹgbẹ ́Afẹ́nifẹ́re kọminú lórí ìwádìí ikú ọmọ Baba Faṣọranti to jẹ olori Afẹ́nifẹ́re – Odumakin

Fẹ́mi Akínṣọlá

Àwọn àgbà ní bí eyín bá n mì pẹkẹ pẹkẹ,erìgì ni kò fálẹ̀ mójúṣe rẹ̀.
Ẹgbe Afenifẹre ti fi ero wọn han lori aijafafa ajọ awọn ọlọpaa lori ẹni to pa Arabinrin Funkẹ Ọlakunrin.
Ninu atẹjade kan ti alukoro ẹgbẹ naa, Yinka Odumakin fi ṣọwọ si awọn akọroyin ni ọjọ Isinmi Osẹ yii lọrọ naa ti jẹyọ.
Wọn ni Ọlọpaa ti n fọwọ yẹpẹrẹ mu ọrọ naa bi wọn ko si ti ri ẹni to pa arabinrin naa titi di asiko yii.
Odumakin sọ pe o ti le ni osu meji bayii ti iṣẹlẹ naa ti waye, ti ko si aridaju pe ajọ Ọlọpaa ti ri ẹnikẹni mu lori ọran naa.

Bi a o ba gbagbe, arabinrin Olufunkẹ Ọlakunrin ti o jẹ ọmọ aṣiwaju ẹgbẹ Afẹnifẹre, Rauben Faṣọnranti, ni awọn agbebọn pa ni popona Ọre si ilu Eko.
Ẹni ti o jẹ aburo si oloogbe naa, Kẹhinde Faṣọnranti ti sọ tẹlẹ nigba ti iṣẹlẹ naa waye pe awọn ọlọpaa ni darandaran lo ṣeku pa arabinrin naa.
Ẹgbe naa ni ọkan ninu awọn ẹri pe Ọlọpaa ko ṣakitiyan ni pe, wọn tete yọnda ọkọ ayọkẹlẹ ti wọn pa arabinrin naa si fun ẹbi i rẹ.
Gẹgẹ bi wọn ti wi, wọn ni Ọlọpaa ko ṣe iwadii kankan lọwọ awakọ to wa arabinrin naa titi di asiko yii.

Siwaju si i, abajade ayẹwo lori bi iku naa ṣe jẹ ko i tii tẹ ẹbi naa lọwọ titi di asiko yii.
Ẹgbẹ naa wa n rọ gbogbo awọn ẹni tọrọ kan lati parọwa si ile – iṣẹ ọlọpaa ki wọn tete fi oju awọn ẹni ibi naa lede ni kiakia,ko le jẹ arikọgbọn fawọn oṣika wole ọla tó kù.

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...