Home / Àṣà Oòduà / Ẹlẹ́wọ̀n 2600 ni ìjọba tú sílẹ̀ ní Nàìjíríà nítorí àrùn apinni léèmí Coronavirus

Ẹlẹ́wọ̀n 2600 ni ìjọba tú sílẹ̀ ní Nàìjíríà nítorí àrùn apinni léèmí Coronavirus

Ìjọba orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti tú ẹlẹ́wọ́n tó lé ní ẹgbẹ̀rún méjì sílẹ̀ ní ọgbà ẹ̀wọ̀n káàkiri orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Aregbesọla ní Ìjọba gbé ìgbésẹ̀ náà láti dẹ́kun ìtànkálẹ̀ àrùn Coronavirus ní Nàìjíríà.

Mínísítà fún ọ̀rọ̀ abẹ́lé lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà náà ni àwọn tí yóó jẹ àǹfààní ìtúsílẹ̀ yìí ni àwọn ẹni tó bá ti kọjá ọgọ́ta ọdún, àwọn aláìsàn , àwọn tó ní àrùn ọpọlọ àti àwọn tó sẹ ẹ̀sẹ̀ kéékèké.

Mínísítà fún ọ̀rọ̀ abẹ́lé lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Rauf Aregbesola ló kéde rẹ̀ ní ibi ayẹyẹ tí wọ́n ti ṣe ìtúsílẹ̀ náà.

About ayangalu

x

Check Also

ojo keji

Ó San Owó Ilé Ìwé Mi Títí Mo Fi Jáde, Ṣùgbọ́n Mo Fi Májèlé San!

Àti ilé ìwé e gírámà ni èmi àti Kọ́lá ti jọ ń fẹ́ ra wa. Àwọn òbí i mi ò kí ń fẹ́ rí Kọ́lá pẹ̀lú u mi nítorí ààfín ni. Nígbà tí mo fẹ́ wo ile ìwé gíga ni bàbá à mi ní àìsàn an rọ́pá, rọsẹ̀,ọpẹ́lọpẹ́ kọ́lá tó san owó ilé ìwé è mi láti ìgbà tí mo wolé ẹ̀kọ́ gíga títí mo fi jádé. Nígbà ti mo lọ ṣe agùnbánirọ̀ mo pàdé sẹ́nátọ kán,èmi àti ẹ̀ sì ...