Home / Àṣà Oòduà / Lai Mohammed fa o̩mo̩ Naijiria létí lórí ìròyìn òfegè

Lai Mohammed fa o̩mo̩ Naijiria létí lórí ìròyìn òfegè

Lai Mohammed fa ọmọ Nàìjíríà létí lórí ìròyìn òfegè

Fẹ́mi Akínṣọlá

Mínísítà ètò ìbáraẹnisọ̀rọ̀ àti Ìròyìn lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Lai Mohammed ti ní ìjọba yóò bẹ̀rẹ̀ ṣí í ṣe àmójútó àtagbà ojú òpó ayélujára báyìí.
Ìgbésẹ̀ yìí ni láti ṣe àfọ̀mọ́ ojú òpó ayélujára kí àdínkù leè bá ayédèrú Ìròyìn àtàwọn ọrọ kòbákùngbé tó ń jẹyọ.


Lai Mohammed sọ ọ̀rọ̀ yìí níbi ìpàdé oníròyìn kan tó wáyé nílùú Abuja
Mínísítà ní èyí kò yọ àwọn oníṣẹ́ ìròyìn sílẹ̀ o. Ó ní ilé iṣẹ́ Ìròyìn tó bá ta féle fèle gan yóó fara kó o.
Àtúnṣe tí wọ́n fẹ́ bẹ̀rẹ̀ yìí yóò tàn dé ojú òpó ayélujára èyí tó sàpèjúwe pé “ó ti kọjá àtúnṣe”.


Lai Mohammed tún ní “láti ìgbà tí a ti ṣe ìfilọ́lẹ̀ ètò àyípadà yìí ni àwọn ọmọ Nàìjíríà kan ti kàn sí wa pé kí a bojú wo bí a ṣe le ṣe ìlanilọyẹ̀ lórí àwọn ayélujára náà a kò sì ní pa eléyìí tì”.
Mohammed ni kò sí ìjọba gidi kan tí yóò jókòó káwọ́ gbera kí ìròyìn òfegè sì máa fò kiri t’òun tọ̀rọ̀ àlùfàǹṣá eléyìí tó leè dáná sun orílẹ̀-èdè láì sí àyẹ̀wò kankan.


“Idi niyii ti ao fi maa koju ayederu iroyin ati ọrọ alufansa ayafi bi a ba to le gbogbo rẹ danu”. O ni tori awọn ti ṣe agbekalẹ igbimọ kan ti aarẹ Buhari fọwọ si lati kọju awọn ọrọ alufansa.

About ayangalu

x

Check Also

ojo keji

Ó San Owó Ilé Ìwé Mi Títí Mo Fi Jáde, Ṣùgbọ́n Mo Fi Májèlé San!

Àti ilé ìwé e gírámà ni èmi àti Kọ́lá ti jọ ń fẹ́ ra wa. Àwọn òbí i mi ò kí ń fẹ́ rí Kọ́lá pẹ̀lú u mi nítorí ààfín ni. Nígbà tí mo fẹ́ wo ile ìwé gíga ni bàbá à mi ní àìsàn an rọ́pá, rọsẹ̀,ọpẹ́lọpẹ́ kọ́lá tó san owó ilé ìwé è mi láti ìgbà tí mo wolé ẹ̀kọ́ gíga títí mo fi jádé. Nígbà ti mo lọ ṣe agùnbánirọ̀ mo pàdé sẹ́nátọ kán,èmi àti ẹ̀ sì ...