Home / Àṣà Oòduà / Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ikú ṣẹlẹ̀ nítorí àṣìṣe àti irọ́ tí China pa lórí coronavirus- Donald Trump

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ikú ṣẹlẹ̀ nítorí àṣìṣe àti irọ́ tí China pa lórí coronavirus- Donald Trump

Ààrẹ Donald Trump ń tú bí ejò ní o , pé ọ̀pọ̀ ẹ̀mí ló ti sọnù látàrí pé China sahun òótọ́ ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ tí àlejò ọ̀ran náà tí fi ọ̀dọ̀ rẹ̀ ṣé bùba , kó tó wá di àǹkóò tí gbogbo àgbáyé n bọ.

Donald Trump tó ń tukọ̀ Ìjọba orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ti kéde pé àsìse orílẹ̀-èdè China ló pa ọ̀pọ̀ èèyàn lórí ọ̀rọ̀ àrùn apinni léèmí coronavirus.

Ó ní àjọ elétò ìlera lágbàáyé náà kò pariwo àrùn apinni léèmí COVID 19 bí ó ṣe yẹ tó nígbà tó bẹ̀rẹ̀ ní China. tó fi di àjàkálẹ̀ àrùn àgbáyé báyìí.

Trump ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìfitónilétí tó jẹ́ irọ́ àti èyí tí kò kún tó ni àjọ WHO kọkọ fi síta lórí àrùn apinni léèmí coronavirus tó bẹ sílẹ̀ ní China, l’éyì tó wá di wàhálà fún gbogbo àgbáyé báyìí, tí kóówá n ṣá kíjo kíjo.

Ṣaájú ni Donald Trump ti kọ́kọ́ gbóríyìn fún ilẹ̀ China lórí bí wọ́n ṣe ṣe nígbà tí orílẹ̀-èdè méjéèjì jọ tọwọ́ bọ ìwé àdéhùn lórí okòwò tuntun.

Trump ní ká sọ pé Àjọ WHO tí tètè gbéra lọ sí Chian tí wọ́n sì ń fi í tó gbogbo agbaye létí bó ṣe yẹ lórí ọ̀rọ̀ àrùn yìí ni, ó ṣeéṣe kí ó má gbilẹ̀ tó báyìí l’ágbàáyé.

O ní aṣiṣe àwọn méjéèjì yìí ló mú ẹ̀mí ọ̀pọ̀ lọ nílọ̀ọ́po ìlọ́po yìí.

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...