Home / Àṣà Oòduà / Àlùfá tọ́ bá ọmọ ọdún méje sùn, wẹ̀wọ̀n ọdún Márùn- ún ní ìpínlẹ̀ Ekiti

Àlùfá tọ́ bá ọmọ ọdún méje sùn, wẹ̀wọ̀n ọdún Márùn- ún ní ìpínlẹ̀ Ekiti

Ọjọ́ gbogbo n t’olè, ọjọ́ kan n t’olóhun.
Ìjọba ìpínlẹ̀ Ekiti tífìtàn balẹ̀ bí wọ́n ṣe jẹ́ ìpínlẹ̀ àkọ́kọ́ tí yóò bẹ̀rẹ̀ láti máa dárúkọ ọ̀daràn afipá bánilòpọ̀ hàn àti láti máa dójú tì wọ́n.

Gómìnà ìpínlẹ̀ náà Kayode Fayemi gbé e jáde lójú òpó twitter rẹ̀ pé àsìkò ti tó láti máa fi ojú aṣebi hàn lásìkò tó gbé àwòrán ẹni ọ̀wọ̀ Asateru Gabriel ti ìjọ St Andrew Anglican Ifinsin -Ekiti nígbà kan.

Gabriel ti fọjú ba ilé ẹjọ ó si jẹ̀bi ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan, nítori ìdí èyí yóò maa ṣẹ̀wọ̀n ọdún márùn ní ọgbà ẹ̀wọ̀n Ìjọba ní Ado Ekiti fún ẹ̀sùn ìfipá bá ọmọ ọdún méje lòpọ̀.

Ní bayiì orúkọ rẹ̀ ti wọ ìwé àkọsílẹ̀ àwọn olùfipábánilòpọ̀ ní ilé ìṣẹ́ ìdajọ́.

Èyí jẹ́ ìpínlẹ̀ Gúúsù- ìwọ̀ -oòrùn àkọ́kọ́ tí yóò gbé ìgbesẹ̀ yìí.

Fẹ́mi Akínṣọlá
Iroyinowuro

About ayangalu

x

Check Also

ojo keji

Ó San Owó Ilé Ìwé Mi Títí Mo Fi Jáde, Ṣùgbọ́n Mo Fi Májèlé San!

Àti ilé ìwé e gírámà ni èmi àti Kọ́lá ti jọ ń fẹ́ ra wa. Àwọn òbí i mi ò kí ń fẹ́ rí Kọ́lá pẹ̀lú u mi nítorí ààfín ni. Nígbà tí mo fẹ́ wo ile ìwé gíga ni bàbá à mi ní àìsàn an rọ́pá, rọsẹ̀,ọpẹ́lọpẹ́ kọ́lá tó san owó ilé ìwé è mi láti ìgbà tí mo wolé ẹ̀kọ́ gíga títí mo fi jádé. Nígbà ti mo lọ ṣe agùnbánirọ̀ mo pàdé sẹ́nátọ kán,èmi àti ẹ̀ sì ...