Home / Àṣà Oòduà / APC kò ní ì ṣe ìdìbò ní ìpínlẹ̀ Òǹdó àyàfi.. Olùdíje kan

APC kò ní ì ṣe ìdìbò ní ìpínlẹ̀ Òǹdó àyàfi.. Olùdíje kan


APC kò ní ì ṣe ìdìbò ní ìpínlẹ̀ Òǹdó àyàfi.. Olùdíje kan

Láìpẹ́ yìí ni ìròyìn kàn pé ìgbìmọ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressive Congress (APC) tó ń ṣe àyẹ̀wò àwọn olùdíje lábẹ́ ẹgbẹ́ náà sọ pé Segun Abraham ni kò kójó òṣùwọ̀n tó nínú àwọn tó ń díje nítori náà ni won ṣe yọ.

Segun Abraham jẹ́ ọ̀kan lára àwọn méjìlá tó ń dije lábẹ́ àsíá ẹgbẹ́ APC tó sì ti gbá ìwé láti fi èrò rẹ̀ hàn pé, òun ṣetan láti kópa nínú ìdìbò abẹ́lé ẹgbẹ́ náà ti yóò wáye ní Ogúnjọ́, Oṣù Keje ọdún yìí.

Sùgbọ́n nínú ìfọ̀rọ̀wáni lẹ́nu wò tí akọròyìn ṣe fún olùdíje náà, Ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé títí di àsìkò yìí, ìgbìmọ̀ kò ti fi tó òun léti pé òun ni wọ́n yọ.

Títí di àsìkò yìí mí ò ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìgbìmọ̀ àyẹ̀wò pé èmì ni wọ́n yọ, tàbi ki wọ́n kọ lẹta nípa rẹ, wọ́n ni, wọ́n ni, ní mò ń gbọ́.”

Àwọn tí wọ́n jọ díje ni Joseph Olusola Iji, Odimayo Okunjimi, Olayide Owolabi Adelami, Isaacs Duerimini Kekemeke, Olusola Oke Alex, lfeoluwa Olusola Oyedele àti Olajumoke Olubusola Anifowoshe.

Àwọn tó kù ni Awodeyi Akinsehinwa Akinola Colinus, Olubukola Adetula, Dr. Abraham Olusegun Michael, Gomina Rotimi Akeredolu ati Dokita Nathaniel Adojutelegan.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...