Home / Àṣà Oòduà / Aregbesola sedaro Hon. Makinde to doloogbe

Aregbesola sedaro Hon. Makinde to doloogbe

Gomina ipinle Osun, Ogbeni Rauf Aregbesola ti ranse ibanikedun si idile Hon Makinde Oladejo Samson to doloogbe lojo Aiku to koja yii, 27/12/15. Hon Makinde, omo egbe PDP, to je okan lara awon omo ile igbimo asofin ipinle Osun lo jade laye leni odun mejidinlaadota (48) leyin aisan ranpe.

Iku Hon Makinde, eni ti n soju Aarin-gbungbun Ife nile igbimo asofin, ni gomina Aregbe se alaye re gege bi ajalu nla eleyii ti enikeni ko reti rara ni asiko yii. Ogbeni Aregbe ko sai tun ranse ibanikedun si egbe PDP ati awon eniyan ti Makinde n soju.

“Bi o tile je wi pe ibanuje ni lati padanu odo bi Onarebu Makinde, sugbon ohun to daju niku; gbogbo wa la dagbada iku. Ki Olorun Oba mimo ba wa te si afefe rere,” Ogbeni Aregbe fi kun leta ibanikedun re bee.

About oodua

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

*

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...