Home / Àṣà Oòduà / Ilé ẹjọ́ kòtẹ́mílọ́rùn yọ alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC Adams Oshiomhole nípò

Ilé ẹjọ́ kòtẹ́mílọ́rùn yọ alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC Adams Oshiomhole nípò

Ilé ẹjọ́ kòtẹ́mílọ́rùn yọ alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC Adams Oshiomhole nípò–

Ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn ti ilú Àbújá ti yẹ àga mọ́ alága ẹgbẹ́ òṣèlú APC, Adams Oshiomhole nídìí

Ìgbìmọ̀ ẹlẹ́ni mẹ́tà ti adájọ́ Eunice Onyemanam sójú fún ni wọ́n fẹnu kò láti jan idájọ́ tí ilé ẹjọ́ ti kọ́kọ́ dá tẹ́lẹ̀ lóntẹ̀

Sáájú ni Oshiomhole ti pe ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn lórí ìdájọ́ tí àdájọ Abubakar Yahaya sì dájọ pé kí ìdájọ́ náà dúró náà kí ó ṣì máa ṣe alága lọ́ títí ìdájọ́ ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn yóò ṣe fìdímúlẹ̀.

Adájọ́ Onyemanam tó dárí ẹjọ́ tó wáyé l’ọ́jọ́ ìṣègùn ló dá ẹjọ́ náà ló fídí rẹ̀ múlẹ̀ pé ìdájọ́ ilé ẹjọ́ kékeré tó yọ Adams Oshiohmole gẹ́gẹ́ bí alágá nínú ọṣù kẹta ọdún yìí ṣe nǹkan tó yẹ àti pé, ẹjọ́ kòtẹ́mílọ́rùn tí Oshiomhole pè kò fìdì múlẹ̀.

Fẹ́mi Akínṣọlá

About ayangalu

x

Check Also

IGP usman

Ọkùnrin tí àwọn adigunjalè yìnbọn mọ́ ní ọjà Bodija ṣì wà láyé — Ọlọ́pàá

Fẹ́mi Akínṣọlá Ìròyìn òkèrè, bí ò lé, a dín.Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ti ṣàlàyé bí ìdigunjalè kan tí ìròyìn sọ pé ó gba ẹ̀mí èèyàn kan ṣe wáyé ní ọjà Bódìjà nílùú Ìbàdàn. Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Adéwálé Òṣífẹ̀sọ̀, sọ nínú àtẹ̀jáde tó fi síta lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún pé lọ́jọ́ ẹtì ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀. Ó ní arákùnrin kan, Abubakar Ibrahim, ni àwọn adigunjalè kọlù ní nǹkan bíi aago mẹ́ta ku ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, tí wọ́n sì yìnbọn mọ́ ọ kí wọ́n ...